Publicidade

Salmos 110

Ti Dafidi. Saamu.

1 Olúwa sọ fún Olúwa mi pé,

"Ìwọ jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún mi,

títí èmi yóò fi sọ àwọn ọ̀tá rẹ

di àpótí ìtìsẹ̀ rẹ."

2 Olúwa yóò na ọ̀pá agbára rẹ̀

láti Sioni wá, ìwọ jẹ ọba láàrín àwọn ọ̀tá rẹ.

3 Àwọn ènìyàn rẹ jẹ́ ọ̀rẹ́ àtinúwá

ní ọjọ́ ìjáde ogun rẹ, nínú ẹwà mímọ́,

láti inú òwúrọ̀ wá ìwọ ni ìrì ẹwà rẹ.

4 Olúwa ti búra,

kò sì í yí ọkàn padà pé,

"Ìwọ ni àlùfáà,

ní ipasẹ̀ Melkisedeki."

5 Olúwa, ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ ni

yóò lu àwọn ọba bolẹ̀ ni ọjọ́ ìbínú rẹ̀.

6 Yóò ṣe ìdájọ́ láàrín kèfèrí,

yóò kún ibùgbé wọn pẹ̀lú òkú ara;

yóò fọ́n àwọn olórí ká sí orí ilẹ̀ ayé tí ó gbòòrò.

7 Yóò mu nínú odò ṣíṣàn ní ọ̀nà:

nítorí náà ni yóò ṣe gbé orí sókè.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-