Publicidade

Salmos 111

1 Ẹ máa yin Olúwa.

Èmi yóò máa yin Olúwa pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi,

ní àwùjọ àwọn olóòtítọ́, àti ní ìjọ ènìyàn.

2 Iṣẹ́ Olúwa tóbi, àwọn tí ó ní inú dídùn, ń ṣe àṣàrò nínú rẹ̀.

3 Iṣẹ́ rẹ̀ ni ọláńlá àti ògo:

àti òdodo rẹ̀ dúró láéláé.

4 Ó ti ṣe iṣẹ́ ìyanu rẹ̀, láti máa rántí:

Olúwa ni olóore-ọ̀fẹ́ àti pé ó kún fún àánú.

5 Ó ti fi oúnjẹ fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀:

òun ń rántí májẹ̀mú rẹ̀.

6 Ó ti fihan àwọn ènìyàn rẹ̀ agbára iṣẹ́ rẹ̀

láti fún wọn ní ilẹ̀ ìlérí ní ìní.

7 Iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ jẹ́ òtítọ́ àti ìdájọ́;

gbogbo òfin rẹ̀ sì dájú.

8 Wọ́n dúró láé àti láé,

ní òtítọ́ àti òdodo ni a ṣe wọ́n.

9 Ó rán ìràpadà sí àwọn ènìyàn rẹ̀:

ó pàṣẹ májẹ̀mú rẹ̀ títí láé,

mímọ́ àti ọ̀wọ̀ ni orúkọ rẹ̀.

10 Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìpilẹ̀ṣẹ̀ ọgbọ́n:

òye dáradára ni yóò máa ṣe òfin rẹ̀,

ìyìn rẹ̀ dúró láé.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-