Publicidade

Salmos 127

Orin fún ìgòkè. Ti Solomoni.

1 Bí kò ṣe pé Olúwa bá kọ́ ilé náà

àwọn tí ń kọ́ ọ ń ṣiṣẹ́ lásán ni;

bí kò ṣe pé Olúwa bá pa ìlú mọ́, olùṣọ́ jí lásán.

2 Asán ni fún ẹ̀yin ti ẹ dìde ní kùtùkùtù

láti pẹ́ dùbúlẹ̀, láti jẹ oúnjẹ làálàá;

bẹ́ẹ̀ ni ó ń fi ìre fún olùfẹ́ rẹ̀ lójú ọ̀run.

3 Kíyèsi i, àwọn ọmọ ni ìní Olúwa:

ọmọ inú sì ni èrè rẹ̀.

4 Bí ọfà ti rí ní ọwọ́ alágbára,

bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ èwe.

5 Ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí apó rẹ̀ kún fún wọn;

ojú kì yóò tì wọ́n,

ṣùgbọ́n wọn yóò ṣẹ́gun àwọn ọ̀tá ní ẹnu-ọ̀nà.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-