Publicidade

Salmos 29

Saamu ti Dafidi.

1 Ẹ fi fún Olúwa, ẹ̀yin ẹ̀dá ọ̀run,

ẹ fi fún Olúwa, ògo àti alágbára.

2 Fi fún Olúwa, àní ògo orúkọ rẹ̀;

sin Olúwa nínú ẹwà ìwà mímọ́.

3 Ohùn Olúwa n ré àwọn omi kọjá;

Ọlọ́run ògo sán àrá,

Olúwa san ara.

4 Ohùn Olúwa ní agbára;

ohùn Olúwa kún fún ọláńlá.

5 Ohùn Olúwa fa igi kedari;

Olúwa náà ló fọ́ igi kedari Lebanoni ya.

6 Ó mú Lebanoni fo bí i ọmọ màlúù,

àti Sirioni bí ọmọ àgbáǹréré.

7 Ohùn Olúwa ń ya

bí ọwọ́ iná mọ̀nà.

8 Ohùn Olúwa ń mi aginjù.

Olúwa mi aginjù Kadeṣi.

9 Ohùn Olúwa ní ó lọ igi óákù, ó n mú abo àgbọ̀nrín bí,

ó sì bọ́ igi igbó sí ìhòhò.

Àti nínú tẹmpili rẹ̀ gbogbo ohùn wí pé, "Ògo!"

10 Olúwa jókòó, Ó sì jẹ ọba lórí ìṣàn omi;

Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ gẹ́gẹ́ bí Ọba títí láéláé.

11 Olúwa fi agbára fún àwọn ènìyàn rẹ̀;

bùkún àwọn ènìyàn rẹ̀ pẹ̀lú àlàáfíà.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-