Publicidade

Salmos 104

1 Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi.

Olúwa Ọlọ́run mi, ìwọ tóbi jọjọ;

ọlá àti ọláńlá ni ìwọ wọ̀ ní aṣọ.

2 Ìwọ fi ìmọ́lẹ̀ bo ara rẹ gẹ́gẹ́ bí aṣọ;

ó tẹ ọ̀run bí títẹ́ ẹní,

3 ìwọ tí ó fi omi ṣe ìtì igi àjà ìyẹ̀wù rẹ.

Ìwọ tí o ṣe àwọsánmọ̀ ní kẹ̀kẹ́ ogun rẹ

ìwọ tí ó ń rìn lórí apá ìyẹ́ afẹ́fẹ́.

4 Ó fi ẹ̀fúùfù ṣe àwọn ìránṣẹ́ rẹ,

ọ̀wọ́-iná ni àwọn olùránṣẹ́ rẹ.

5 O fi ayé gúnlẹ̀ lórí àwọn ìpìlẹ̀;

tí a kò le è mì láéláé.

6 Ìwọ fi ibú omi bò ó mọ́lẹ̀ bí aṣọ;

àwọn omi sì dúró lórí àwọn òkè ńlá.

7 Ṣùgbọ́n nípa ìbáwí rẹ ni àwọn omi lọ,

nípa ohùn àrá rẹ ni wọ́n sálọ.

8 wọ́n sàn kọjá lórí àwọn òkè,

wọ́n sọ̀kalẹ̀ lọ sí àwọn pẹ̀tẹ́lẹ̀,

sí ibi tí ìwọ ti yàn fún wọn.

9 Ìwọ gbé òpin tí wọn kò lè kọjá rẹ̀ kálẹ̀;

láéláé ni wọ́n kò ní lè bo ayé mọ́lẹ̀ lẹ́ẹ̀kan sí i.

10 Ìwọ mú kí ìsun da omi sí àwọn àfonífojì;

tí ó ń sàn láàrín àwọn òkè.

11 Wọ́n fún gbogbo àwọn ẹranko igbó ní omi

àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ń pa òǹgbẹ wọn.

12 Àwọn ẹyẹ ojú òfúrufú tẹ́ ìtẹ́ wọn lẹ́gbẹ̀ẹ́ omi

wọ́n ń kọrin láàrín àwọn ẹ̀ka.

13 Ó bu omi rin àwọn òkè láti ìyẹ̀wù rẹ̀ wá;

a tẹ́ ayé lọ́rùn nípa èso iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.

14 Ó mú kí koríko hù jáde fún àwọn ẹranko láti jẹ

àti àwọn ewébẹ̀ fún ènìyàn láti lò,

kí ó lè mú oúnjẹ jáde láti ilẹ̀ wá.

15 Ọtí wáìnì tí ó ń mú ọkàn ènìyàn yọ̀,

òróró láti mú ojú rẹ̀ tan,

àti àkàrà láti ra ọkàn rẹ̀ padà.

16 Àwọn igi Olúwa ni a bu omi rin dáradára,

kedari ti Lebanoni tí ó gbìn.

17 Níbẹ̀ ní àwọn ẹyẹ ṣe ìtẹ́ wọn

bí ó ṣe tí àkọ̀ ni, orí igi gíga ni ilé rẹ̀.

18 Àwọn òkè gíga ni ààbò fún àwọn ewúrẹ́ igbó;

àti àwọn àlàpà jẹ́ ààbò fún àwọn ehoro.

19 Òṣùpá jẹ́ àmì fún àkókò

oòrùn sì mọ ìgbà tí yóò wọ̀.

20 Ìwọ mú òkùnkùn wá, ó sì di òru,

nínú èyí tí gbogbo ẹranko igbó ń rìn kiri.

21 Kìnnìún ń bú ramúramù fún ohun ọdẹ wọn

wọ́n sì ń wá oúnjẹ wọn láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.

22 Oòrùn ràn, wọ́n sì kó ara wọn jọ,

wọn padà lọ dùbúlẹ̀ sí ihò wọn.

23 Ọkùnrin jáde lọ sí iṣẹ́ wọn,

àti sí làálàá rẹ̀ títí di àṣálẹ́.

24 Iṣẹ́ rẹ ti pọ̀ tó, Olúwa!

Nínú ọgbọ́n ni ìwọ ṣe gbogbo wọn:

ayé kún fún àwọn ìṣẹ̀dá á rẹ.

25 Bẹ́ẹ̀ ni Òkun yìí tí ó tóbi, tí ó sì ni ìbú,

tí ó kún fún àwọn ẹ̀dá alààyè ní ìsàlẹ̀ láìníye

ohun alààyè tí tóbi àti kékeré.

26 Níbẹ̀ ni ọkọ̀ ń lọ síwá sẹ́yìn,

àti Lefitani, tí ìwọ dá láti ṣe àríyá nínú rẹ̀.

27 Àwọn wọ̀nyí ń wò ọ́

láti fún wọn ní oúnjẹ wọn lákòókò rẹ̀.

28 Nígbà tí ìwọ bá fi fún wọn,

wọn yóò kó jọ;

nígbà tí ìwọ bá la ọwọ́ rẹ̀,

a tẹ́ wọn lọ́rùn pẹ̀lú ohun rere.

29 Nígbà tí ìwọ bá pa ojú rẹ mọ́

ara kò rọ̀ wọ́n

nígbà tí ìwọ bá mú ẹ̀mí wọn lọ,

wọn ó kú, wọn ó sì padà sí erùpẹ̀.

30 Nígbà tí ìwọ rán ẹ̀mí rẹ,

ni a dá wọn,

ìwọ sì tún ojú ayé ṣe.

31 Jẹ́ kí ògo Olúwa wà pẹ́ títí láé;

kí inú Olúwa kí ó dùn ní ti iṣẹ́ rẹ̀,

32 ẹni tí ó wo ayé, tí ó sì wárìrì,

ẹni tí ó fọwọ́ tọ́ àwọn òkè, tí wọ́n yọ èéfín.

33 Ní gbogbo ayé mi ní n ó kọrin sí Olúwa:

èmi ó kọrin ìyìn sí Olúwa

níwọ̀n ìgbà tí mo wà láààyè.

34 Jẹ́ kí ẹ̀kọ́ mi kí ó tẹ́ ọ lọ́rùn

bí mo ti ń yọ̀ nínú Olúwa.

35 Ṣùgbọ́n kí ẹlẹ́ṣẹ̀ kúrò láyé

kí ènìyàn búburú má sì sí mọ́.

Yin Olúwa, ìwọ ọkàn mi.

Yin Olúwa.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-16_18-40-07-