Publicidade

Salmos 122

Orin fún ìgòkè. Ti Dafidi.

1 Inú mi dùn nígbà tí wọ́n wí fún mi pé,

"Ẹ jẹ́ kí á lọ sílé Olúwa."

2 Ẹsẹ̀ wa yóò dúró ní ẹnu ibodè rẹ,

ìwọ Jerusalẹmu.

3 Jerusalẹmu, ìwọ tí a kọ́ bí ìlú

tí o fi ara mọ́ra pọ̀ ṣọ̀kan.

4 Níbi tí àwọn ẹ̀yà máa ń gòkè lọ,

àwọn ẹ̀yà Olúwa,

ẹ̀rí fún Israẹli,

láti máa dúpẹ́ fún orúkọ Olúwa.

5 Nítorí ibẹ̀ ni a gbé ìtẹ́ ìdájọ́ kalẹ̀,

àwọn ìtẹ́ ilé Dafidi.

6 Gbàdúrà fún àlàáfíà Jerusalẹmu;

àwọn tí ó fẹ́ ọ yóò ṣe rere.

7 Kí àlàáfíà kí ó wà nínú odi rẹ̀,

àti ìre nínú ààfin rẹ̀.

8 Nítorí àwọn ọkùnrin àti àwọn ẹgbẹ́ mi

èmi yóò wí nísinsin yìí pé,

kí àlàáfíà kí ó wà nínú rẹ̀.

9 Nítorí ilé Olúwa Ọlọ́run wa,

èmi yóò máa wá ìre rẹ̀.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-