Publicidade

Salmos 150

1 Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.

Ẹ fi ìyìn fún Ọlọ́run ní ibi mímọ́ rẹ̀,

ẹ yìn ín nínú agbára ọ̀run rẹ̀.

2 Ẹ yìn ín fún iṣẹ́ agbára rẹ̀.

Ẹ yìn ín fún títóbi rẹ̀ tí ó tayọ̀.

3 Ẹ fi ohùn ìpè yìn ín.

Ẹ fi ohun èlò orin yìn ín.

4 Ẹ fi ohun èlò orin àti ijó yìn ín

fi ohun èlò orin olókùn àti ìpè yìn ín,

5 Ẹ yìn ín pẹ̀lú aro olóhùn òkè,

ẹ yìn ín lára aro olóhùn gooro.

6 Jẹ́ kí gbogbo ohun tí ó ní ẹ̀mí yin Olúwa.

Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-