Publicidade

Salmos 84

Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí ti gittiti. Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu.

1 Ibùgbé rẹ̀ ti lẹ́wà tó,

Olúwa àwọn ọmọ-ogun!

2 Ọkàn mi ń ṣàfẹ́rí nítòótọ́

ó tilẹ̀ pòǹgbẹ fún àgbàlá Olúwa

àyà mi àti ara mi ń kọrin ayọ̀

sí Ọlọ́run alààyè.

3 Nítòótọ́ ológoṣẹ́ ri ilé,

ẹyẹ alápáǹdẹ̀dẹ̀ tẹ́ ìtẹ́ fún ara rẹ̀,

níbi tí yóò máa pa ọmọ rẹ̀ mọ́ sí:

ibùgbé ní tòsí pẹpẹ rẹ̀,

Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ọba mí àti Ọlọ́run mi.

4 Ìbùkún ní fún àwọn tí ó ń gbé inú ilé rẹ;

wọn ó máa yìn ọ́ títí láé.

5 Ìbùkún ni fún àwọn tí agbára wọn wà nínú rẹ

àwọn tí wọ́n gbé ọkàn lé bíbẹ ibi mímọ́ wò.

6 Àwọn tí ń la àfonífojì omijé lọ

wọn sọ ọ́ di kànga

àkọ́rọ̀ òjò sì fi ìbùkún bò ó.

7 Wọ́n ń lọ láti ipa dé ipá

títí tí ọ̀kọ̀ọ̀kan fi farahàn níwájú Ọlọ́run ní Sioni.

8 Gbọ́ àdúrà mi, Olúwa Ọlọ́run Alágbára;

tẹ́tí sí mi, Ọlọ́run Jakọbu.

9 Wo asà wa, Ọlọ́run;

fi ojú àánú wò àwọn ẹni àmì òróró rẹ.

10 Dídára ní ọjọ́ kan ní ààfin rẹ

ju ẹgbẹ̀rún (1,000) ọjọ́ lọ;

èmi o kúkú máa ṣe aṣọ́nà nínú ilé Ọlọ́run mi

jù láti gbé ní àgọ́ àwọn ènìyàn búburú.

11 Nítorí Olúwa Ọlọ́run jẹ́ òòrùn àti asà;

Olúwa fún ni ní ojúrere àti ọlá;

kò sí ohun rere kan tí yóò fàsẹ́yìn

fún àwọn tí ó rìn ní àìlábùkù.

12 Olúwa àwọn ọmọ-ogun,

ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-