Publicidade

Salmos 66

Fún adarí orin. Orin. Saamu.

1 Ẹ hó ìhó ayọ̀ sí Ọlọ́run, ẹ̀yin ilẹ̀ gbogbo!

2 Ẹ kọrin ọlá orúkọ rẹ̀;

ẹ kọrin ìyìnsí i.

3 Ẹ wí fún Ọlọ́run pé, "Ìwọ ti ní ẹ̀rù tó nínú iṣẹ́ rẹ!

Nípa ọ̀pọ̀ agbára rẹ

ni àwọn ọ̀tá rẹ yóò fi sìn ọ́.

4 Gbogbo ayé ń wólẹ̀ fún ọ;

wọn ń kọrin ìyìn sí ọ,

wọ́n ń kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ." Sela.

5 Ẹ wá wo ohun tí Ọlọ́run ṣe,

iṣẹ́ rẹ̀ ti ní ẹ̀rù tó sí àwọn ọmọ ènìyàn!

6 Ó yí òkun padà sí ilẹ̀ gbígbẹ,

wọ́n fi ẹsẹ̀ rin inú omi kọjá,

níbẹ̀ ni àwa yọ̀ nínú rẹ̀.

7 Ó ń jẹ ọba títí láé nípa agbára rẹ̀,

ojú rẹ̀ ń wo orílẹ̀-èdè

kí àwọn ọlọ̀tẹ̀ má ṣe gbé ara wọn ga. Sela.

8 Ẹ yin Ọlọ́run wa, ẹ̀yin ènìyàn,

jẹ́ kí a mú ni gbọ́ ohùn ìyìn rẹ̀;

9 Ó ti dá ààbò bo ẹ̀mí wa,

kò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ wa kí ó yẹ̀.

10 Nítorí ìwọ, Ọlọ́run, dán wa wò;

ìwọ dán wa bí a tí ń dán fàdákà wò.

11 Ìwọ mú wa wá sínú ẹ̀wọ̀n

o sì di ẹrù lé ẹ̀yìn wa.

12 Ìwọ mú àwọn ènìyàn gún wá ní orí

àwa la iná àti omi kọjá

ṣùgbọ́n ìwọ mú wa dé ibi ọ̀pọ̀.

13 Èmi ó wá sí tẹmpili rẹ pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun,

kí n sì mú ẹ̀jẹ́ mi ṣẹ sí ọ,

14 ẹ̀jẹ́ tí ètè mi jẹ́, tí ẹnu mi sì sọ

nígbà tí mo wà nínú ìṣòro.

15 Èmi ó rú ẹbọ sísun ọlọ́ràá sí ọ,

àti ẹbọ ọ̀rá àgbò;

èmi ó rú akọ màlúù àti ewúrẹ́. Sela.

16 Ẹ wá gbọ́ gbogbo ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run;

ẹ jẹ́ kí n sọ ohun tí ó ṣe fún mi.

17 Mo fi ẹnu mi kígbe sókè sí i,

ìyìn rẹ̀ wà ní ẹnu mi.

18 Bí èmi bá gba ẹ̀ṣẹ̀ ní àyà mi,

Olúwa kì yóò gbọ́ ohùn mi;

19 ṣùgbọ́n Ọlọ́run gbọ́ nítòótọ́

ó ti gbọ́ ohùn mi nínú àdúrà.

20 Ìyìn ni fún Ọlọ́run

ẹni tí kò kọ àdúrà mi

tàbí mú ìfẹ́ rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi!

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-16_18-40-07-