Publicidade

Salmos 125

Orin fún ìgòkè.

1 Àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé Olúwa yóò dàbí òkè Sioni,

tí a kò lè ṣí ní ìdí, bí kò ṣe pé ó dúró láéláé.

2 Bí òkè ńlá ti yí Jerusalẹmu ká,

bẹ́ẹ̀ ni Olúwa yí ènìyàn ká

láti ìsinsin yìí lọ àti títí láéláé.

3 Nítorí tí ọ̀pá àwọn ènìyàn búburú

kì yóò bà lé ìpín àwọn olódodo;

kí àwọn olódodo kí ó máa ba à

fi ọwọ́ wọn lé ẹ̀ṣẹ̀.

4 Olúwa ṣe rere fún àwọn ẹni rere,

àti fún àwọn tí àyà wọn dúró ṣinṣin.

5 Bí ó ṣe ti irú àwọn tí wọn yà sí ipa ọ̀nà wíwọ́ wọn;

Olúwa yóò jẹ́ kí wọn lọ pẹ̀lú àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.

Ṣùgbọ́n àlàáfíà yóò wà lórí Israẹli.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-