Publicidade

Salmos 2

1 Èéṣe tí àwọn orílẹ̀-èdè fi ń dìtẹ̀,

àti tí àwọn ènìyàn ń ṣe rìkíṣí asán?

2 Àwọn ọba ayé péjọpọ̀

àti àwọn ìjòyè gbìmọ̀ pọ̀

Olúwa àti sí ẹni àmì òróró rẹ̀.

3 Wọ́n sọ pé, "Ẹ jẹ́ kí a fa ẹ̀wọ̀n wọn já,

kí a sì ju ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ wọn nù."

4 Ẹni tí ó gúnwà lórí ìtẹ́ lọ́run rẹ́rìn-ín;

Olúwa fi wọ́n rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà.

5 Nígbà náà ni yóò bá wọn wí ní ìbínú rẹ̀

yóò sì dẹ́rùbà wọ́n ní ìrunú rẹ̀, ó wí pé,

6 "Èmi ti fi ọba mi sí ipò

lórí Sioni, òkè mímọ́ mi."

7 Èmi yóò sì kéde ìpinnu Olúwa:

Ó sọ fún mi pé, "Ìwọ ni ọmọ mi;

lónìí, èmi ti di baba rẹ.

8 Béèrè lọ́wọ́ mi,

Èmi yóò jẹ́ kí orílẹ̀-èdè di ìní rẹ,

òpin ilé ayé yóò sì jẹ́ ogún rẹ.

9 Ìwọ yóò fi ọ̀pá irin ṣe àkóso wọn

ìwọ yóò sì rún wọn wómúwómú bí ìkòkò amọ̀."

10 Nítorí náà, ẹ̀yin ọba, ẹ jẹ́ ọlọ́gbọ́n;

ẹ gbọ́ ìkìlọ̀ ẹ̀yin alákòóso ayé.

11 Ẹ sin Olúwa pẹ̀lú ìbẹ̀rù

ẹ sì máa yọ̀ pẹ̀lú ìwárìrì.

12 Fi ẹnu ko ọmọ náà ní ẹnu, kí ó má ba à bínú,

kí ó má ba à pa yín run ní ọ̀nà yín,

nítorí ìbínú rẹ̀ lè ru sókè ní ẹ̀ẹ̀kan.

Ìbùkún ni fún gbogbo àwọn tí ó fi í ṣe ibi ìsádi wọn.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-