Publicidade

Salmos 11

Fún adarí orin. Ti Dafidi.

1 Ìgbẹ́kẹ̀lé mi wà nínú Olúwa.

Báwo ní ẹ̀yin ó ṣe sọ fún ọkàn mi pé,

"Fò gẹ́gẹ́ bi ẹyẹ lọ si orí òkè rẹ.

2 Wò ó nítorí náà, ènìyàn búburú fa ọfà rẹ̀;

wọn ti fi ọfà wọn sí ojú okùn

láti tafà níbi òjìji

sí àyà ẹni ìdúró ṣinṣin.

3 Nígbà tí ìpìlẹ̀ bá bàjẹ́

kí ni olódodo yóò ṣe?"

4 Olúwa ń bẹ nínú tẹmpili mímọ́ rẹ̀;

Olúwa ń bẹ lórí ìtẹ́ rẹ̀ ní ọ̀run.

Ó ń wo àwọn ọmọ ènìyàn;

ojú rẹ̀ ń yẹ̀ wọ́n wò.

5 Olúwa ń yẹ olódodo wò,

ṣùgbọ́n ènìyàn búburú àti àwọn tí o fẹ́ ìwà ipá

ni ọkàn rẹ̀ kórìíra.

6 Sí orí àwọn ènìyàn búburú ni yóò rọ̀jò

ẹ̀yín iná àti imí-ọjọ́ tí ń jó;

àti ìjì gbígbóná ní yóò jẹ ìpín wọn.

7 Nítorí, olódodo ní Olúwa,

o fẹ́ràn òdodo;

ẹni ìdúró ṣinṣin yóò sì rí i.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-