Publicidade

Salmos 12

Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí ti ṣeminiti. Saamu ti Dafidi.

1 Ràn wá lọ́wọ́, Olúwa, nítorí ẹni ìwà-bí-Ọlọ́run kò sí mọ́;

olóòtítọ́ tí pòórá kúrò láàrín àwọn ènìyàn.

2 Olúkúlùkù ń parọ́ fún aládùúgbò rẹ̀;

ètè èké wọn ń sọ ẹ̀tàn.

3 Olúwa kí ó gé ètè èké wọn

àti gbogbo ahọ́n ìfọ́nnu

4 tí ó wí pé,

"Àwa ó borí pẹ̀lú ahọ́n wa;

àwa ní ètè wa, ta ni ọ̀gá wa?"

5 "Nítorí ìnilára àwọn aláìlágbára àti ìkérora àwọn aláìní,

Èmi yóò dìde nísinsin yìí," ni Olúwa wí.

"Èmi yóò dáàbò bò wọ́n lọ́wọ́ àwọn tí ń ṣe àrankàn wọn."

6 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì jẹ aláìlábùkù,

gẹ́gẹ́ bí fàdákà tí a yọ́ nínú ìléru amọ̀,

tí a sọ di mímọ́ nígbà méje.

7 Olúwa, ìwọ yóò pa wá mọ́

kí o sì gbà wá lọ́wọ́ àwọn ènìyàn wọ̀nyí títí láé.

8 Àwọn ènìyàn búburú ń rin ìrìn fáàrí kiri

nígbà tí wọn ń bọ̀wọ̀ fún òsì láàrín àwọn ènìyàn.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-