Publicidade

Salmos 87

Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu. Orin.

1 Ó ti fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ sọlẹ̀ sórí òkè mímọ́;

2 Olúwa fẹ́ràn ẹnu-ọ̀nà Sioni

ju gbogbo ibùgbé Jakọbu lọ.

3 Ohun ológo ni a sọ nípa rẹ̀,

ìlú Ọlọ́run,

4 "Èmi ó dárúkọ Rahabu àti Babeli

láàrín àwọn tí ó jẹ́wọ́ mi:

Filistia pẹ̀lú, àti Tire, pẹ̀lú Kuṣi,

yóò sọ pé, ‘Èyí ni a bí ní Sioni.’ "

5 Nítòótọ́, ti Sioni ni a ó sọ,

"Eléyìí àti eléyìí ni a bí nínú rẹ̀,

àti Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo ni yóò fìdí rẹ̀ múlẹ̀."

6 Olúwa yóò kọ nínú àkọsílẹ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀:

"Eléyìí ni a bí ní Sioni."

7 Àti àwọn olórin àti àwọn tí ń lu

ohun èlò orin yóò wí pé,

"Gbogbo orísun mi ń bẹ nínú rẹ."

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-