Publicidade

Salmos 52

Fún adarí orin. Maskili ti Dafidi. Nígbà tí Doegi ará Edomu tọ Saulu lọ láti sọ fún pé, "Dafidi wà ní ilé Ahimeleki."

1 Èéṣe tí ìwọ fi ń ṣe féfé nínú ìwà ìkà, ìwọ alágbára ọkùnrin?

Èéṣe tí ìwọ fi ń gbéraga nígbà gbogbo,

ìwọ ẹni ẹ̀gàn níwájú Ọlọ́run?

2 Ahọ́n rẹ̀ ń gbìmọ̀ ìparun;

ó dàbí abẹ mímú,

ìwọ ẹni tí ń hùwà ẹ̀tàn.

3 Ìwọ fẹ́ràn ibi ju ìre lọ,

àti èké ju kí ó sọ òtítọ́ lọ.

4 Ìwọ fẹ́ràn ọ̀rọ̀ ìpanilára gbogbo,

ìwọ ahọ́n ẹ̀tàn!

5 Ọlọ́run yóò sì lù ọ́ bolẹ̀ láéláé,

yóò sì dì ọ́ mú,

yóò sì já ọ kúrò ni ibùjókòó rẹ,

yóò sì fà ọ́ tu kúrò lórí ilẹ̀ alààyè. Sela.

6 Àwọn olódodo yóò rí, wọn yóò sì bẹ̀rù

wọn yóò sì rẹ́rìn-ín rẹ̀, wí pé,

7 "Èyí ni ọkùnrin náà ti kò fi Ọlọ́run ṣe agbára rẹ̀,

bí kò ṣe ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọrọ̀ rẹ̀ ni ó gbẹ́kẹ̀lé,

ó sì mu ara rẹ̀ le nínú ìwà búburú rẹ̀."

8 Ṣùgbọ́n èmi dàbí igi Olifi

tí ó gbilẹ̀ nínú ilé Ọlọ́run;

èmi gbẹ́kẹ̀lé ìfẹ́ Ọlọ́run tí kì í kùnà

láé àti láéláé.

9 Èmi yóò yìn ọ títí fún ohun tí ó ti ṣe;

èmi ní ìrètí nínú orúkọ rẹ,

nítorí orúkọ rẹ dára.

Èmi yóò yìn ọ́ níwájú àwọn ènìyàn mímọ́.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-