Publicidade

Oséias 11

Ìfẹ́ Ọlọ́run sí Israẹli

1 "Nígbà tí Israẹli wà ní ọmọdé mo fẹ́ràn rẹ̀,

mo sì pe ọmọ mi jáde láti Ejibiti wá.

2 Bí a ti ń pe wọn,

bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ń sá kúrò lọ́dọ̀ mi,

wọn rú ẹbọ sí Baali,

wọn sì fi tùràrí jóná sí ère fínfín.

3 Lóòtítọ́ mo kọ́ Efraimu pẹ̀lú ní ìrìn

mo di wọ́n mú ní apá,

ṣùgbọ́n wọn kò mọ̀

pé mo ti mú wọn láradá.

4 Mo fi okùn ènìyàn fà wọ́n

àti ìdè ìfẹ́.

Mo mú àjàgà kúrò ni ọrùn wọn,

Mo sì fi ara balẹ̀ fún wọn ni oúnjẹ.

5 "Ṣé wọn ò wá ní padà sí Ejibiti bí.

Ṣé Asiria kò sì ní jẹ ọba lé wọn lórí bí

nítorí pé wọ́n kọ̀ jálẹ̀ láti ronúpìwàdà?

6 Idà yóò kọ mọ̀nà ní gbogbo ìlú wọn

yóò si bá gbogbo irin ẹnu odi ìlú wọn jẹ́

yóò sì fi òpin sí gbogbo èrò wọn.

7 Àwọn ènìyàn mi ti pinnu láti pẹ̀yìndà kúrò lọ́dọ̀ mi

bí wọ́n tilẹ̀ pè wọ́n sọ́dọ̀ Ọ̀gá-ògo jùlọ,

kò ní gbé wọn ga rárá.

8 "Báwo ni èmi ó ṣe fi ọ́ sílẹ̀, Efraimu?

Báwo ni èmi ó ṣe yọ̀ǹda rẹ̀, Israẹli?

Báwo ni mo ṣe lè ṣe ọ bi i Adma?

Báwo ni mo ṣe lè ṣe ọ bi i Seboimu?

Ọkàn mi yípadà nínú mi

àánú mi sì ru sókè.

9 Èmi kò ni mú ìbínú gbígbóná mi ṣẹ,

tàbí kí èmi wá sọ Efraimu di ahoro.

Nítorí pé èmi ni Ọlọ́run, àní, èmi kì í ṣe ènìyàn.

Ẹni mímọ́ láàrín yín,

Èmi kò ní í wá nínú ìbínú.

10 Wọn yóò máa tẹ̀lé Olúwa;

òun yóò bú ramúramù bí i kìnnìún.

Nígbà tó bá bú,

àwọn ọmọ rẹ yóò wá ní ìwárìrì láti ìwọ̀-oòrùn.

11 Wọn ó wá pẹ̀lú ẹ̀rù

bí i ẹyẹ láti Ejibiti,

bí i àdàbà láti Asiria,

Èmi ó mú wọn padà sí ilé wọn,"

ni Olúwa wí.

Ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli

12 Efraimu tí fi irọ́ yí mi ká

ilé Israẹli pẹ̀lú ẹ̀tàn.

Ṣùgbọ́n Juda sì dúró ṣinṣin pẹ̀lú Ọlọ́run.

Ó sì ṣe olóòtítọ́ sí Ẹni mímọ́ Israẹli.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-