Publicidade

Oséias 6

Àìronúpìwàdà Israẹli

1 "Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a padà sọ́dọ̀ Olúwa

ó ti fà wá ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ

ṣùgbọ́n yóò mú wa láradá

Ó ti pa wá lára

ṣùgbọ́n yóò dí ojú ọgbẹ́ wa.

2 Lẹ́yìn ọjọ́ méjì, yóò sọ wá jí

ní ọjọ́ kẹta yóò mú wa padà bọ̀ sípò

kí a ba à le wá gbé níwájú rẹ̀.

3 Ẹ jẹ́ kí a mọ Olúwa;

ẹ jẹ́ kí a tẹ̀síwájú láti mọ̀ ọ́n.

Gẹ́gẹ́ bí oòrùn ṣe ń yọ,

yóò jáde;

yóò tọ̀ wá wá bí òjò,

bí òjò àkọ́rọ̀ ti ń bomirin ilẹ̀."

4 "Kí ni èmi ó ṣe pẹ̀lú rẹ, Efraimu?

Kí ni èmi ó ṣe pẹ̀lú rẹ, Juda?

Ìfẹ́ rẹ dàbí ìkùùkuu òwúrọ̀

bí ìrì ìdájí tí ó kọjá lọ kíákíá.

5 Nítorí náà ni mo ṣe gé e yín sí wẹ́wẹ́ láti ọwọ́ àwọn wòlíì,

Mo pa yín pẹ̀lú ọ̀rọ̀ ẹnu mi,

ìdájọ́ mi tàn bí i mọ̀nàmọ́ná lórí yín.

6 Nítorí àánú ni mo fẹ́, kì í ṣe ẹbọ;

àti ìmọ̀ Ọlọ́run ju ọrẹ ẹbọ sísun lọ.

7 Bí i Adamu, wọ́n da májẹ̀mú

wọ́n jẹ́ aláìṣòótọ́ sí mi níbẹ̀.

8 Gileadi jẹ́ ìlú àwọn ènìyàn búburú

tí ń ṣiṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀, a sí ti fi ẹ̀ṣẹ̀ bà á jẹ́.

9 Bí adigunjalè ṣe ń ba ní bùba de àwọn ènìyàn

bẹ́ẹ̀ ni àwọn àlùfáà, ń parapọ̀;

tí wọ́n sì ń pànìyàn lójú ọ̀nà tó lọ sí Ṣekemu,

tí wọ́n sì ń dá ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ti ni lójú.

10 Mo ti rí ohun tó ba ni lẹ́rù

ní ilé Israẹli.

Níbẹ̀ Efraimu, fi ara rẹ̀ fún àgbèrè

Israẹli sì di aláìmọ́.

11 "Àti fún ìwọ, Juda,

a ti yan ọjọ́ ìkórè rẹ.

"Nígbà tí mo bá fẹ́ dá ohun ìní àwọn ènìyàn mi padà,

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-