Publicidade

Oséias 14

Ìwòsàn ń bẹ fún àwọn tó ronúpìwàdà

1 Yípadà ìwọ Israẹli sí Olúwa Ọlọ́run rẹ.

Ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ló fa ìparun rẹ!

2 Ẹ gba ọ̀rọ̀ Olúwa gbọ́,

kí ẹ sì yípadà sí Olúwa.

Ẹ sọ fún un pé,

"Darí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá

kí o sì fi oore-ọ̀fẹ́ gbà wá,

kí àwa kí ó lè fi ètè wa sán an fún ọ

3 Asiria kò le gbà wá là;

a kò ní í gorí ẹṣin ogun.

A kò sì ní tún sọ ọ́ mọ́ láé, ‘Àwọn ni òrìṣà wa’

sí àwọn ohun tí ó fi ọwọ́ wa ṣe;

nítorí pé lọ́dọ̀ rẹ ni àwọn aláìní baba tí ń rí àánú."

4 "Èmi wo àgàbàgebè wọn sàn,

Èmi ó sì fẹ́ràn wọn, lọ́fẹ̀ẹ́,

nítorí ìbínú mi ti yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn.

5 Èmi o dàbí ìrì sí Israẹli,

wọn o sì yọ ìtànná bi ewéko lílì.

Bi kedari ti Lebanoni yóò si ta gbòǹgbò.

6 Àṣẹ̀ṣẹ̀yọ ẹ̀ka rẹ̀ yóò dàgbà,

dídán ẹwà yóò rẹ̀ dànù bí igi olifi.

Òórùn rẹ yóò sì dàbí igi kedari ti Lebanoni.

7 Àwọn ènìyàn yóò tún padà gbé lábẹ́ òjijì rẹ̀.

Yóò rúwé bi ọkà.

Yóò sì yọ ìtànná bi àjàrà,

òórùn rẹ yóò dàbí ti wáìnì Lebanoni.

8 Ìwọ Efraimu, kín ló tún kù tí mo ní ṣe pẹ̀lú ère òrìṣà?

Èmi ó dá a lóhùn, èmi ó sì ṣe ìtọ́jú rẹ.

Mo dàbí igi junifa tó ń fi gbogbo ìgbà tutù,

èso tí ìwọ ń so si ń wá láti ọ̀dọ̀ mi."

9 Ta ni ọlọ́gbọ́n? Òun yóò mòye àwọn nǹkan wọ̀nyí.

Ta a ní ó mọ̀? Òun yóò ní ìmọ̀ wọn.

Títọ́ ni ọ̀nà Olúwa

àwọn olódodo si ń rìn nínú wọn,

ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́tẹ̀ ni yóò kọsẹ̀ nínú wọn.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-