Publicidade

Salmos 47

Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu.

1 Ẹ pàtẹ́wọ́, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn

ẹ hó sí Ọlọ́run pẹ̀lú orin ayọ̀ tó rinlẹ̀.

2 Báwo ni Olúwa Ọ̀gá-ògo ti ní ẹ̀rù tó

ọba ńlá lórí gbogbo ayé.

3 Ṣe ìkápá àwọn orílẹ̀-èdè lábẹ́ wa

àwọn ènìyàn lábẹ́ ẹsẹ̀ wa

4 Ó mú ilẹ̀ ìní wa fún wa,

ọlá Jakọbu, ẹni tí ó fẹ́ wa.

5 Ọlọ́run tó gòkè lọ tí òun tayọ̀,

Olúwa ti òun ti ariwo ìpè.

6 Ẹ kọrin ìyìn sí Ọlọ́run, ẹ kọrin ìyìn.

Ẹ kọrin ìyìn sí ọba wa, ẹ kọrin ìyìn!

7 Nítorí Ọlọ́run ni ọba gbogbo ayé,

ẹ kọrin ìyìn pẹ̀lú Saamu!

8 Ọlọ́run jẹ ọba lórí gbogbo kèfèrí;

Ọlọ́run jókòó lórí ìtẹ́ ìwà mímọ́ rẹ̀.

9 Àwọn aládé ayé kó ara wọn jọ

gẹ́gẹ́ bí ènìyàn Ọlọ́run Abrahamu

nítorí asà ayé ti Ọlọ́run ni,

òun ni ó ga jùlọ.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-