Publicidade

Salmos 64

Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi.

1 Gbóhùn mi, Ọlọ́run, bí mo ti ń sọ àròyé mi

pa ọkàn mi mọ́ kúrò lọ́wọ́ ẹ̀rù àwọn ọ̀tá.

2 Pa mí mọ́ kúrò lọ́wọ́ ìmọ̀ ìkọ̀kọ̀ àwọn ènìyàn búburú

kúrò nínú ọ̀pọ̀ igbe lọ́wọ́ ìrúkèrúdò oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.

3 Wọ́n pọ́n ahọ́n wọn bí idà,

wọ́n sì fa ọrun wọn le láti tafà wọn, àní ọ̀rọ̀ kíkorò.

4 Wọ́n tafà ní ìkọ̀kọ̀ sí àwọn aláìlẹ́ṣẹ̀:

wọ́n tafà si lójijì, wọn kò sì bẹ̀rù.

5 Wọ́n, gba ara wọn níyànjú nínú èrò búburú,

wọ́n sọ̀rọ̀ lórí dídẹkùn sílẹ̀ ní ìkọ̀kọ̀

wọ́n wí pé, "Ta ni yóò rí wa?"

6 Wọ́n gbìmọ̀ àìṣòdodo, wọ́n wí pé,

"A wa ti parí èrò tí a gbà tán!"

Lóòótọ́ àyà àti ọkàn ènìyàn kún fún àrékérekè.

7 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò ta wọ́n ní ọfà;

wọn ó sì gbọgbẹ́ lójijì.

8 Ahọ́n wọn yóò sì dojú ìjà kọ wọ́n, yóò sì run wọ́n,

gbogbo ẹni tí ó bá rí wọn yóò sì mi orí fún wọn.

9 Gbogbo ènìyàn yóò máa bẹ̀rù

wọn ó kéde iṣẹ́ Ọlọ́run

wọn ó dúró lé ohun tí ó ṣe.

10 Jẹ́ kí olódodo kí ó yọ̀ nínú Olúwa

yóò sì rí ààbò nínú rẹ̀.

Gbogbo ẹni ìdúró ṣinṣin ní ọkàn yóò máa yìn ín.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-