Publicidade

Salmos 75

Fún adarí orin. Tí ohùn, "Má ṣe parun." Saamu ti Asafu. Orin.

1 A fi ìyìn fún ọ, Ọlọ́run,

a yìn ọ́, nítorí orúkọ rẹ súnmọ́ tòsí;

àwọn ènìyàn ń sọ ti ìyanu rẹ.

2 Ìwọ wí pé, "Mo yan àkókò ìyàsọ́tọ̀;

Èmi ni ẹni tí ń ṣe ìdájọ́ òdodo.

3 Nígbà tí ayé àti àwọn ènìyàn ibẹ̀ wárìrì,

Èmi ni mo di òpó rẹ̀ mú ṣinṣin.

4 Èmí wí fún àwọn agbéraga pé,

ẹ má ṣe gbéraga mọ́;

àti sí ènìyàn búburú;

ẹ má ṣe gbé ìwo yín sókè.

5 Ẹ má ṣe gbe ìwo yín sókè sí ọ̀run;

ẹ má ṣe sọ̀rọ̀ pẹ̀lú ọrùn líle."

6 Nítorí ìgbéga kò ti ìlà-oòrùn wá

tàbí ní ìwọ̀-oòrùn,

bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe láti gúúsù wá.

7 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run ni olùdájọ́;

Ó ń rẹ ẹnìkan sílẹ̀, ó sì ń gbé ẹlòmíràn ga.

8 Ní ọwọ́ Olúwa ni ago kan wà,

ọtí wáìnì náà sì pọ́n, ó kún fún àdàlú,

ó fún ọtí àdàlú tí a pò mọ́ òórùn dídùn tí ó tú jáde,

àwọn ènìyàn búburú ayé gbogbo mú u pátápátá.

9 Ṣùgbọ́n èmi, ó máa ròyìn rẹ títí láé;

èmi ó kọrin ìyìn sí Ọlọ́run Jakọbu.

10 Èmi ó gé ìwo gbogbo ènìyàn búburú,

ṣùgbọ́n ìwo àwọn olódodo ni a ó gbéga.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-