Publicidade

Salmos 137

1 Ní ẹ̀bá odò Babeli, níbẹ̀ ni àwa gbé jókòó

àwa sì sọkún nígbà tí àwa rántí Sioni.

2 Àwa fi dùùrù wa kọ́ sí orí igi wílò,

tí ó wà láàrín rẹ̀.

3 Nítorí pé níbẹ̀ ni àwọn

tí ó kó wa ní ìgbèkùn béèrè orin lọ́wọ́ wa,

àti àwọn tí ó ni wá lára béèrè ìdárayá;

wọn wí pé, "Ẹ kọ orin Sioni kan fún wa!"

4 Àwa ó ti ṣe kọ orin

Olúwa ní ilẹ̀ àjèjì

5 Jerusalẹmu, bí èmi bá gbàgbé rẹ

jẹ́ kí ọwọ́ ọ̀tún mi kí ó gbàgbé ìlò rẹ̀.

6 Bí èmi kò bá rántí rẹ,

jẹ́ kí ahọ́n mi kí ó lẹ̀ mọ́ èrìgì mi;

bí èmi kò bá fi Jerusalẹmu ṣáájú

olórí ayọ̀ mi gbogbo.

7 Olúwa rántí ọjọ́ Jerusalẹmu,

lára àwọn ọmọ Edomu,

àwọn ẹni tí ń wí pé,

"Wó o palẹ̀, wó o palẹ̀ dé ìpìlẹ̀ rẹ̀!"

8 Ìwọ, ọmọbìnrin Babeli, ẹni tí a ó parun;

ìbùkún ni fún ẹni tí ó san án fún ọ

bí ìwọ ti rò sí wa.

9 Ìbùkún ni fún ẹni tí ó mú ọmọ wẹ́wẹ́ rẹ

tí ó sì fi wọ́n ṣán òkúta.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-