Publicidade

Salmos 57

Fún adarí orin. Ní ohùn "Má ṣe parun." Ti Dafidi. Miktamu. Nígbà tí ó sá níwájú Saulu lọ sínú ihò òkúta.

1 Ṣàánú fún mi, Ọlọ́run, ṣàánú fún mi,

nítorí nínú rẹ ni ààbò ọkàn mí wà.

Èmi o fi ààbò mí sí ibi ìyẹ́ apá rẹ

títí tí ewu yóò fi kọjá lọ.

2 Mo kígbe sókè sí Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo jùlọ,

sí Ọlọ́run tó ń pa májẹ̀mú rẹ̀ mọ́ fún mi.

3 Òun yóò ránṣẹ́ láti ọ̀run wá,

yóò sì gbà mí, bí ẹni tí ń fẹ́ gbé mi mì

tilẹ̀ ń kẹ́gàn mi.

Ọlọ́run yóò rán àánú rẹ̀ àti òdodo rẹ̀ jáde.

4 Mo wà ní àárín àwọn kìnnìún;

mo dùbúlẹ̀ ni abẹ́ àwọn ẹ̀dá búburú,

àwọn ènìyàn tí eyín wọn dàbí ọ̀kọ̀ àti ọfà

ẹni tí ahọ́n rẹ̀ jẹ́ idà mímú.

5 Kí a yìn ọ́ Ọlọ́run, ju ọ̀run lọ,

kí ògo rẹ kò ju ti gbogbo ayé lọ.

6 Wọ́n ti ta àwọ̀n sílẹ̀ fún ẹsẹ̀ mi:

a tẹ orí ọkàn mi ba nínú ìtìjú,

wọ́n gbẹ́ kòtò sí ọ̀nà mi:

ṣùgbọ́n wọ́n ti jì síbẹ̀ fún ara wọn.

7 Ọkàn mi ti múra Ọlọ́run;

ọkàn mi ti múra, èmi ó kọrin, èmi ó si máa kọrin ìyìn.

8 Jí, ìwọ ọkàn mi!

Jí, ohun orin èlò àti dùùrù!

Èmi tìkára mi, yóò sì jí ní kùtùkùtù.

9 Èmi ó máa yìn ọ́, Olúwa, láàrín àwọn orílẹ̀-èdè;

èmi ó máa kọrin sí ọ láàrín àwọn ènìyàn.

10 Nítorí títóbi ní ìfẹ́ rẹ, tí ó dé ọ̀run;

òtítọ́ rẹ tàn dé àwọsánmọ̀.

11 Gbígbéga ni ọ́, Ọlọ́run, ju àwọn ọ̀run lọ;

kí ògo rẹ kí ó ju gbogbo ayé lọ.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-