Publicidade

Salmos 24

Ti Dafidi. Saamu.

1 Ti Olúwa ni ilẹ̀, àti ẹ̀kún rẹ̀,

ayé àti àwọn tí ó tẹ̀dó sínú rẹ̀;

2 nítorí ó fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lélẹ̀ lórí òkun

ó sì gbé e kalẹ̀ lórí àwọn ìṣàn omi.

3 Ta ni yóò gun orí òkè Olúwa lọ?

Ta ni yóò dúró ní ibi mímọ́ rẹ̀?

4 Ẹni tí ó ní ọwọ́ mímọ́ àti àyà funfun,

ẹni tí kò gbé ọkàn rẹ̀ sókè sí asán

tí kò sì búra èké.

5 Òun ni yóò rí ìbùkún gbà láti ọ̀dọ̀ Olúwa,

àti òdodo lọ́wọ́ Ọlọ́run ìgbàlà rẹ̀.

6 Èyí ni ìran àwọn tí ń ṣe àfẹ́rí rẹ̀,

tí ń ṣe àfẹ́rí rẹ̀, Ọlọ́run Jakọbu. Sela.

7 Ẹ gbé orí yín sókè, háà! Ẹ̀yin ọ̀nà;

kí á sì gbe yín sókè, ẹyin ìlẹ̀kùn ayérayé!

Kí ọba ògo le è wọlé.

8 Ta ni ọba ògo náà?

Olúwa tí ó lágbára tí ó sì le,

Olúwa gan an, tí ó lágbára ní ogun.

9 Gbé orí yín sókè, ẹyin ọ̀nà;

kí a sì gbé e yín sókè, ẹ̀yin ìlẹ̀kùn ayérayé,

kí Ọba ògo le è wọlé wá.

10 Ta ni Ọba ògo náà?

Olúwa àwọn ọmọ-ogun

Òun ni Ọba ògo náà. Sela.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-