Publicidade

Salmos 130

Orin fún ìgòkè.

1 Láti inú ibú wá ni

èmi ń ké pè é ọ́ Olúwa

2 Olúwa, gbóhùn mi,

jẹ́ kí etí rẹ kí o tẹ́ sílẹ̀ sí ohùn ẹ̀bẹ̀ mi.

3 Olúwa, ìbá ṣe pé kí ìwọ máa sàmì ẹ̀ṣẹ̀,

Olúwa, tá ni ìbá dúró.

4 Nítorí ìdáríjì wà lọ́dọ̀ rẹ,

kí a lè máa bẹ̀rù rẹ.

5 Èmi dúró de Olúwa, ọkàn mi dúró,

àti nínú ọ̀rọ̀ rẹ ni èmi ń ṣe ìrètí.

6 Ọkàn mi dúró de Olúwa,

ju àwọn tí ń ṣọ́nà òwúrọ̀ lọ,

àní ju àwọn tí ń ṣọ́nà òwúrọ̀ lọ.

7 Israẹli, ìwọ ní ìrètí ní ti Olúwa:

nítorí pé lọ́dọ̀ Olúwa ni àánú wà,

àti lọ́dọ̀ rẹ̀ ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìdáǹdè wà.

8 Òun ó sì dá Israẹli ní ìdè

kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ gbogbo.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-16_18-40-07-