Publicidade

Salmos 54

Fún adarí orin. Pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn. Maskili ti Dafidi. Nígbà tí àwọn ará Sifi lọ sọ fún Saulu pé, "Dafidi sá pamọ́ sọ́dọ̀ wa?"

1 Gbà mí, Ọlọ́run nípa orúkọ rẹ:

dá mi láre nípa agbára rẹ.

2 Gbọ́ àdúrà mi, Ọlọ́run;

fi etí sí ọ̀rọ̀ ẹnu mi.

3 Àwọn agbéraga àlejò dìde sí mí.

Àwọn aninilára sì ń wá mi láti pa,

àwọn ẹni tí kò ka Ọlọ́run sí ní ojú wọn.

4 Kíyèsi i Ọlọ́run ni olùrànlọ́wọ́ mi;

Olúwa ní ẹni tí ó mú mi dúró,

pa wọ́n run nínú òtítọ́ rẹ.

5 Jẹ́ kí ibi padà sẹ́yìn sí àwọn tí ń sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí mi;

pa wọ́n run nínú òtítọ́ rẹ.

6 Èmí yóò rú ẹbọ àtinúwá sí ọ,

èmi yóò yin orúkọ rẹ, Olúwa,

nítorí tí ó dára.

7 Nítorí tí ó yọ mí kúrò nínú ibi gbogbo

ojú mi ti wo ìṣẹ́gun lórí ọ̀tá mi.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-