Publicidade

Salmos 40

Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu.

1 Mo fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ dúró de Olúwa;

ó sì dẹtí sí mi, ó sì gbọ́ ẹkún mi.

2 Ó fà mí yọ gòkè

láti inú ihò ìparun,

láti inú ẹrẹ̀ pọ̀tọ̀pọ́tọ̀,

ó sì fi ẹsẹ̀ mi lé orí àpáta,

ó sì jẹ́ kí ìgbésẹ̀ mi wà láìfòyà.

3 Ó fi orin tuntun sí mi lẹ́nu,

àní orin ìyìn sí Ọlọ́run wa.

Ọ̀pọ̀ yóò rí i wọn yóò sì bẹ̀rù,

wọn yóò sì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa.

4 Ayọ̀ ni fún àwọn wọ̀n-ọn-nì

tí ó fi Olúwa ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé wọn

tí wọn kò sì yípadà sí agbéraga,

tàbí àwọn tí ó yapa

lọ sí ọ̀dọ̀ ọlọ́run mìíràn.

5 Olúwa Ọlọ́run mi,

ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn iṣẹ́ ìyanu tí ìwọ ti ṣe.

Àwọn ohun tí ìwọ ti ṣètò sílẹ̀ fún wa;

ni ẹnikẹ́ni kò le kà wọ́n fún ọ lẹ́sẹẹsẹ,

tí èmi yóò sì sọ̀rọ̀ wọn,

wọ́n ju ohun tí

ènìyàn le è kà lọ.

6 Ẹbọ àti ẹran ẹbọ ni ìwọ kò fẹ́,

ìwọ ti ṣí mi ní etí.

Ọrẹ ẹbọ sísun àti ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀

ni ìwọ kò béèrè.

7 Nígbà náà ni mo wí pé,

"Èmi nìyí;

nínú ìwé kíká ni

a kọ ọ nípa tèmi wí pé.

8 Mo ní inú dídùn

láti ṣe ìfẹ́ ẹ̀ rẹ,

ìwọ Ọlọ́run mi,

òfin rẹ̀ ń bẹ ní àyà mi."

9 Èmi ti sọ ìròyìn ayọ̀ ti ìgbàlà

láàrín àwùjọ ńlá;

wò ó,

èmi kò pa ètè mi mọ́,

gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti mọ̀,

ìwọ Olúwa.

10 Èmi kò fi ìrànlọ́wọ́ ìgbàlà sin ní àyà mi;

èmí ti sọ̀rọ̀ nípa òtítọ́ àti ìgbàlà rẹ.

Èmi kò sì pa ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti òtítọ́ rẹ̀ mọ́

kúrò láàrín àwọn ìjọ ńlá.

11 Ìwọ má ṣe, fa àánú rẹ tí ó rọ́nú sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ mi Olúwa;

jẹ́ kí ìṣeun ìfẹ́ rẹ àti òtítọ́ rẹ

kí ó máa pa mi mọ́ títí ayérayé.

12 Nítorí pé àìníye ibi

ni ó yí mi káàkiri,

ẹ̀ṣẹ̀ mi sì dì mọ́ mi,

títí tí èmi kò fi ríran mọ́;

wọ́n pọ̀ ju irun orí mi lọ,

àti wí pé àyà mí ti kùnà.

13 Jẹ́ kí ó wù ọ́,

ìwọ Olúwa,

láti gbà mí là;

Olúwa,

yára láti ràn mí lọ́wọ́.

14 Gbogbo àwọn wọ̀n-ọn-nì ni kí ojú kí ó tì

kí wọn kí ó sì dààmú;

àwọn tí ń wá ọkàn mi láti parun

jẹ́ kí a lé wọn padà sẹ́yìn kí a sì dójútì wọ́n,

àwọn tí ń wá ìpalára mi.

15 Jẹ́ kí àwọn tí ó wí fún mi pé, "Háà! Háà!"

ó di ẹni à fi ọwọ́ rọ́ sẹ́yìn nítorí ìtìjú wọn.

16 Jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ń wá ọ

kí ó máa yọ̀

kí inú wọn sì máa dùn sí ọ;

kí gbogbo àwọn tí ó sì fẹ́ ìgbàlà rẹ

kí o máa wí nígbà gbogbo pé,

"Gbígbéga ni Olúwa!"

17 Bí ó ṣe ti èmi ni,

tálákà àti aláìní ni èmi,

ṣùgbọ́n Olúwa ń ṣe ìrántí mi.

Ìwọ ni olùrànlọ́wọ́ mi

àti ìgbàlà mi;

má ṣe jẹ́ kí ó pẹ́,

ìwọ Ọlọ́run mi.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-