Publicidade

Salmos 70

Fún adarí orin. Ti Dafidi. Ẹ̀bẹ̀.

1 Yára, Ọlọ́run, láti gbà mí là,

Olúwa, wá kánkán láti ràn mí lọ́wọ́.

2 Kí àwọn tí ń wá ọkàn mi

kí a dójútì wọ́n, kí wọn sì dààmú;

kí àwọn tó ń wá ìparun mi

yí ẹ̀yìn padà nínú ìtìjú.

3 Kí a pa wọ́n ní ẹ̀yìn dà fún èrè

ìtìjú àwọn tí ń wí pé, "Háà! Háà!"

4 Ṣùgbọ́n kí àwọn tí ó ń wá ọ ó máa yọ̀

kí inú wọn kí ó sì máa dùn nípa rẹ,

kí àwọn tí ó ń fẹ́ ìgbàlà rẹ máa wí pé,

"Jẹ́ kí a gbé Ọlọ́run ga!"

5 Ṣùgbọ́n mo jẹ́ òtòṣì àti aláìní;

wa kánkán sí ọ̀dọ̀ mi, Ọlọ́run.

Ìwọ ni olùrànlọ́wọ́ àti olùdáǹdè mi;

Olúwa, má ṣe dúró pẹ́.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-16_06-50-08-