Publicidade

Salmos 10

1 Èéha ti ṣe, Olúwa, tí ìwọ fi dúró ní òkè réré?

Èéha ti ṣe, tí ìwọ fi ara rẹ pamọ́ ní ìgbà ìpọ́njú?

2 Nínú àrékérekè ni ènìyàn búburú tí mu aláìlera,

ẹni ti ó mú nínú ìdẹ̀kùn àrékérekè rẹ̀.

3 Nítorí ènìyàn búburú ń ṣògo ìfẹ́ inú ọkàn rẹ̀;

Ó bùkún olójúkòkòrò, ó sì ń kẹ́gàn Olúwa.

4 Ènìyàn búburú kò lè rí nínú ìgbéraga rẹ̀;

kò sí ààyè fún Ọlọ́run nínú gbogbo èrò rẹ̀.

5 Ọ̀nà rẹ̀ ń gún régé nígbà gbogbo;

òun ń gbéraga, òfin rẹ̀ sì jìnnà sí i;

òun kẹ́gàn àwọn ọ̀tá rẹ̀.

6 O wí fún ara rẹ̀, "Kò sí ohun tí ó lè mì mí.

Inú mi yóò máa dùn nígbà gbogbo, èmi kò sì ní ní wàhálà."

7 Ẹnu rẹ̀ kún fún ègún àti irọ́ àti ìtànjẹ;

wàhálà àti ohun búburú wà lábẹ́ ahọ́n rẹ̀.

8 Ó lúgọ ní bùba nítòsí ìletò.

Ò gọ níbi ìkọ̀kọ̀ láti pa aláìṣẹ̀.

Ojú rẹ̀ ń ṣọ́ àwọn tálákà ní ìkọ̀kọ̀.

9 Ó ba ní ní bùba bí i kìnnìún nínú pàǹtí;

Ó ba ní bùba láti mú àwọn aláìní ìrànwọ́;

ó mú àwọn aláìlólùrànlọ́wọ́, ó sì wọ́ wọn lọ sínú àwọ̀n rẹ̀.

10 Ó ba, ó rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀;

kí tálákà ba à le bọ́ sí ọwọ́ agbára rẹ̀.

11 Ó wí fún ara rẹ̀, "Ọlọ́run ti gbàgbé;

Ó pa ojú rẹ̀ mọ́, òun kì yóò rí i láéláé."

12 Dìde, Olúwa! Gbé ọwọ́ rẹ sókè, Ọlọ́run.

Má ṣe gbàgbé àwọn olùpọ́njú.

13 Èéṣe tí ènìyàn búburú ṣe ń kẹ́gàn Ọlọ́run?

Èéṣe tí o fi wí nínú ọkàn ara rẹ̀,

"Kò ní pè mí láti ṣe ìṣirò"?

14 Ṣùgbọ́n ìwọ, Ọlọ́run, ni ó rí wàhálà àti ìrora;

Ìwọ rò láti fi sí ọwọ́ rẹ.

Tálákà fi ara rẹ̀ jì fún ọ;

Ìwọ ni olùrànlọ́wọ́ àwọn aláìní baba.

15 Ṣẹ́ apá àwọn ènìyàn búburú àti ènìyàn ibi;

pè é láti wá ṣírò fún ìwà ìkà rẹ̀

tí a kò le è rí.

16 Olúwa ń jẹ ọba láé àti láéláé;

àwọn orílẹ̀-èdè yóò ṣègbé lórí ilé rẹ.

17 Ìwọ́ gbọ́, Olúwa, ìfẹ́ àwọn tí a ni lára;

Ìwọ gbà wọ́n níyànjú, ó sì gbọ́ igbe wọn,

18 láti ṣe ìdájọ́ àwọn aláìní baba àti àwọn ti a ni lára,

kí ọkùnrin, tí ó wà ní ayé,

kí ó má ṣe dẹ́rùbà ni mọ́.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-