Publicidade

Salmos 7

Ṣiggaioni ti Dafidi, èyí tí ó kọ sí Olúwa nípa Kuṣi, ará Benjamini.

1 Olúwa Ọlọ́run mi, ààbò mi wà nínú rẹ;

gba mí là kí o sì tú mi sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn tó ń lé mi,

2 kí wọn ó má ba à fa ọkàn mi ya gẹ́gẹ́ bí kìnnìún,

wọ́n á ya á pẹ́rẹpẹ̀rẹ láìsí ẹni tí yóò gbà mí.

3 Olúwa Ọlọ́run mi, tí èmi bá ṣe èyí

tí ẹ̀bi sì wà ní ọwọ́ mi.

4 bí èmi bá ṣe ibi sí ẹni tí ń wá àlàáfíà pẹ̀lú mi,

tí mo ja ọ̀tá mi lólè láìnídìí,

5 nígbà náà, jẹ́ kí ọ̀tá mi lé mi kí wọn sì mú mi;

jẹ́ kí òun kí ó tẹ ọkàn mi mọ́lẹ̀

kí wọn sì mú mi sùn nínú eruku. Sela.

6 Dìde, Olúwa, nínú ìbínú rẹ;

dìde lòdì sí ìrunú àwọn ọ̀tá mi.

Jí, Ọlọ́run mi; kéde òdodo.

7 Kí ìpéjọ àwọn ènìyàn yíká.

Jọba lórí wọn láti òkè wá.

8 Jẹ́ kí Olúwa ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn.

Ṣe ìdájọ́ mi, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí òdodo mi,

gẹ́gẹ́ bí ìwà òtítọ́, ẹni gíga jùlọ.

9 Ọlọ́run Olódodo,

Ẹni tí ó ń wo inú àti ọkàn,

tí ó ń mú òpin sí ìwà ipá ẹni búburú

tí ó sì ń pa àwọn olódodo mọ́.

10 Ààbò mi ń bẹ lọ́dọ̀ Ọlọ́run,

ẹni tí ń ṣe ìgbàlà òtítọ́ ní àyà.

11 Ọlọ́run ni onídàájọ́ òtítọ́,

Ọlọ́run tí ń sọ ìrunú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́.

12 Bí kò bá yípadà,

Òun yóò pọ́n idà rẹ̀ mú;

ó ti fa ọrun rẹ̀ le ná, ó ti múra rẹ̀ sílẹ̀.

13 Ó ti pèsè ohun ìjà ikú sílẹ̀;

ó ti pèsè ọfà iná sílẹ̀.

14 Ẹni tí ó lóyún ohun búburú,

tí ó sì lóyún wàhálà, ó bí èké jáde.

15 Ẹni tí ó gbẹ́ ọ̀fìn, tí ó kó o jáde

jì sí kòtò tí ó gbẹ́ sílẹ̀.

16 Wàhálà tí ó fà padà sórí rẹ̀;

ìwà ipá rẹ̀ padà sórí ara rẹ̀.

17 Èmi ó fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí òdodo rẹ̀,

èmi ó kọrin ìyìn sí Olúwa Ọ̀gá-ògo jùlọ.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-