Publicidade

Salmos 36

Fún adarí orin. Ti Dafidi ìránṣẹ́ Olúwa.

1 Ìré-òfin-kọjá ènìyàn búburú

jẹ́ kí n mọ̀ nínú ọkàn mi pé,

ìbẹ̀rù Ọlọ́run kò sí

níwájú wọn.

2 Nítorí pé wọ́n pọ́n ara wọn ní ojú ara wọn

títí tí a kò fi le rí ẹ̀ṣẹ̀ wọn láti kórìíra.

3 Ọ̀rọ̀ ẹnu wọn ni ẹ̀ṣẹ̀ òhun ẹ̀tàn;

wọ́n ti fi ọgbọ́n àti ṣíṣe rere sílẹ̀.

4 Wọ́n gbìmọ̀ ìwà ìkà nígbà tí wọ́n wà lórí ibùsùn wọn:

wọ́n gba ọ̀nà tí kò dára

wọn kò sì kọ ọ̀nà ibi sílẹ̀.

5 Ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ, ìwọ Olúwa, ó ga dé ọ̀run,

òtítọ́ ọ̀ rẹ ga dé àwọsánmọ̀.

6 Òdodo rẹ dàbí àwọn òkè Ọlọ́run,

àwọn ìdájọ́ rẹ dàbí ibú ńlá;

ìwọ gba ẹranko àti ènìyàn là, Olúwa.

7 Báwo ni ìṣeun ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ ti tó! Ọlọ́run!

Kí gbogbo ọmọ ènìyàn le sá sí abẹ́ òjìji ìyẹ́ rẹ.

8 Àsè ilé rẹ yóò tẹ́ wọn lọ́rùn gidigidi;

ìwọ yóò sì mú wọn mu nínú odò inú dídùn rẹ.

9 Nítorí pé pẹ̀lú rẹ ni orísun ìyè wà:

nínú ìmọ́lẹ̀ rẹ ni àwa yóò rí ìmọ́lẹ̀.

10 Mú ìṣeun ìfẹ́ ẹ̀ rẹ sí àwọn tí ó mọ̀ ọ́n

àti ìgbàlà rẹ sí àwọn tí ó ní ìdúró ṣinṣin ọkàn!

11 Má ṣe jẹ́ kí ẹsẹ̀ agbéraga kí ó wá sí orí mi,

kí o má sì jẹ́ kí ọwọ́ àwọn ènìyàn búburú sí mi ní ipò.

12 Níbẹ̀ ni àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ gbé ṣubú sí:

a rẹ̀ wọ́n sílẹ̀, wọn kì yóò le è dìde!

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-