Publicidade

Salmos 55

Fún adarí orin. Pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn. Maskili ti Dafidi.

1 Fi etí sí àdúrà mi, Ọlọ́run,

má ṣe fi ojú pa ẹ̀bẹ̀ mi rẹ́:

2 gbọ́ mi kí o sì dá mi lóhùn.

Èrò mi ń dà mí láàmú, èmi sì ń pariwo.

3 Sí ohùn àwọn ọ̀tá ni,

nítorí igbe àwọn ènìyàn búburú;

nítorí wọ́n mú ìjìyà wá sórí mi,

wọ́n sì kẹ́gàn mi nínú ìbínú wọn.

4 Ọkàn mi wà nínú ìrora pẹ̀lú;

ẹ̀rù ikú kọjú ìjà sí mi.

5 Ìbẹ̀rù àti ìwárìrì wa sí ara mi;

ìbẹ̀rù ti bò mí mọ́lẹ̀.

6 Èmi sọ pé, "Èmi ìbá ní ìyẹ́ bí àdàbà!

Èmi ìbá fò lọ kí n sì sinmi.

7 Èmi ìbá sálọ, jìnnà réré,

kí ń sì dúró sí aginjù;

8 èmi ìbá yára lọ́ si ibùgbé mi ní ibi ààbò,

jìnnà kúrò nínú ìjì àti ẹ̀fúùfù líle."

9 Da àwọn ẹni búburú láàmú, Olúwa, da ahọ́n wọn rú,

nítorí èmi rí ìwà agbára àti ìjà ní ìlú náà.

10 Ọ̀sán àti òru ni wọ́n fi ń rìn gbogbo odi kiri;

ìwà ìkà àti èébú wà láàrín rẹ̀.

11 Ìwà búburú ń bẹ ní àárín rẹ̀;

ẹ̀tàn àti èké kò kúrò ní ìgboro rẹ̀.

12 Tí ọ̀tá bá tàbùkù mi,

èmi yóò fi ara mọ́ ọn;

tí ọ̀tá bá gbé ara rẹ̀ ga sí mi,

èmi ìbá sá pamọ́ fún un.

13 Ṣùgbọ́n tí ó bá ṣe ìwọ, ọkùnrin bí ẹgbẹ́ mi,

ẹlẹgbẹ́ mi, àti ọ̀rẹ́ tí ó súnmọ́ mi,

14 pẹ̀lú ẹni tí èmi ti jẹ ìgbádùn adùn ìdàpọ̀,

bí a ṣe ń rìn pẹ̀lú àwùjọ ní ilé Ọlọ́run.

15 Kí ikú kí ó dé bá wọn,

kí wọn ó lọ láààyè sí isà òkú,

jẹ́ kí wọn ó sọ̀kalẹ̀ sí ibojì pẹ̀lú ìpayà,

nítorí tí ìwà búburú ń bẹ ní ibùjókòó wọn, àti nínú wọn.

16 Ṣùgbọ́n èmi pe Ọlọ́run;

Olúwa yóò sì gbà mí.

17 Ní alẹ́, ní òwúrọ̀ àti ní ọ̀sán

èmi sọkún jáde nínú ìpọ́njú,

o sì gbọ́ ohùn mi.

18 Ó rà mí padà láìléwu

kúrò nínú ogun tí ó dìde sí mi,

nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó dìde sí mi.

19 Ọlọ́run yóò gbọ́, yóò sì pọ́n wọn lójú àní,

ẹni tí ó ti jókòó láti ìgbàanì Sela,

nítorí tí wọn kò ní àyípadà,

tí wọn kò sì bẹ̀rù Ọlọ́run.

20 Ọ̀rẹ́ mi yìí ti dalẹ̀ èmi ọ̀rẹ́ rẹ̀;

ó ti ba májẹ̀mú rẹ̀ jẹ́.

21 Ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ kúnná ju òrí-àmọ́,

ṣùgbọ́n ogun wà ni àyà rẹ̀;

ọ̀rọ̀ rẹ̀ fẹ́lẹ́ ju òróró lọ,

ṣùgbọ́n idà fífàyọ ní wọn.

22 Gbé ẹrù rẹ lọ sí ọ̀dọ̀ Olúwa

yóò sì mú ọ dúró;

òun kò ní jẹ́ kí olódodo ṣubú.

23 Ṣùgbọ́n ìwọ, Ọlọ́run, ni yóò mu àwọn ọ̀tá mi

wá sí ihò ìparun;

àwọn ẹni tí òǹgbẹ ẹ̀jẹ̀ ń gbẹ àti ẹni ẹ̀tàn,

kì yóò gbé ààbọ̀ ọjọ́ wọn.

Ṣùgbọ́n fún èmi, èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-