Publicidade

Salmos 126

Orin fún ìgòkè.

1 Nígbà tí Olúwa mú ìkólọ Sioni padà,

àwa dàbí ẹni tí ó ń lá àlá.

2 Nígbà náà ni ẹnu wa kún fún ẹ̀rín,

àti ahọ́n wa kọ orin;

nígbà náà ni wọ́n wí nínú àwọn kèfèrí pé,

Olúwa ṣe ohun ńlá fún wọn.

3 Olúwa ṣe ohun ńlá fún wa;

nítorí náà àwa ń yọ̀.

4 Olúwa mú ìkólọ wa padà,

bí ìṣàn omi ní gúúsù.

5 Àwọn tí ń fi omijé fún irúgbìn

yóò fi ayọ̀ ka.

6 Ẹni tí ń fi ẹkún rìn lọ,

tí ó sì gbé irúgbìn lọ́wọ́,

lóòtítọ́, yóò fi ayọ̀ padà wá,

yóò sì ru ìtí rẹ̀.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-16_18-40-07-