Publicidade

Salmos 144

Ti Dafidi.

1 Ìyìn sí Olúwa àpáta mi,

ẹni tí ó kọ́ ọwọ́ mi fún ogun,

àti ìka mi fún ìjà.

2 Òun ni Ọlọ́run ìfẹ́ mi àti odi alágbára mi,

ibi gíga mi àti olùgbàlà mi, asà mi,

ẹni tí èmi gbẹ́kẹ̀lé,

ẹni tí ó tẹrí àwọn ènìyàn ba lábẹ́ mi.

3 Olúwa, kí ni ènìyàn tí ìwọ fi ń ṣàníyàn fún un,

tàbí ọmọ ènìyàn tí ìwọ fi ń ronú nípa rẹ̀?

4 Ènìyàn rí bí èmi;

ọjọ́ rẹ̀ rí bí òjìji tí ń kọjá lọ.

5 Tẹ ọ̀run rẹ ba, Olúwa, kí o sì sọ̀kalẹ̀;

tọ́ àwọn òkè ńlá wọn yóò sí rú èéfín.

6 Rán mọ̀nàmọ́ná kí ó sì fọ́n àwọn ọ̀tá ká;

ta ọfà rẹ kí ó sì dà wọ́n rú.

7 Na ọwọ́ rẹ sílẹ̀ láti ibi gíga;

gbà mí kí o sì yọ mí nínú ewu

kúrò nínú omi ńlá:

kúrò lọ́wọ́ àwọn ọmọ àjèjì.

8 Ẹnu ẹni tí ó kún fún èké

ẹni tí ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ jẹ́ ìrẹ́jẹ.

9 Èmi yóò kọ orin tuntun sí ọ

Ọlọ́run; lára ohun èlò orin

olókùn mẹ́wàá èmi yóò

kọ orin sí ọ.

10 Òun ni ó fi ìgbàlà fún àwọn ọba,

ẹni tí ó gba Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́wọ́ idà ìpanilára.

Lọ́wọ́ pípanirun. 11 Gbà mí kí o sì yọ mí nínú ewu

kúrò lọ́wọ́ àwọn ọmọ àjèjì

tí ẹnu wọn kún fún èké,

tí ọwọ́ ọ̀tún wọn jẹ́ ọwọ́ ọ̀tún èké.

12 Kí àwọn ọmọkùnrin wa

kí ó dàbí igi gbígbìn tí ó dàgbà ni ìgbà èwe wọn,

àti ọmọbìnrin wa yóò dàbí òpó ilé

tí a ṣe ọ̀nà sí bí àfarawé ààfin.

13 Àká wa yóò kún

pẹ̀lú gbogbo onírúurú oúnjẹ

àgùntàn wa yóò pọ̀ si ní ẹgbẹ̀rún,

ní ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ní oko wa:

14 àwọn màlúù wa yóò ru ẹrù wúwo

kí ó má sí ìkọlù,

kí ó má sí ìkólọ sí ìgbèkùn,

kí ó má sí i igbe ìpọ́njú ní ìgboro wa.

15 Ìbùkún ni fún àwọn ènìyàn náà tí ó wà ní irú ipò bẹ́ẹ̀,

ìbùkún ni fún àwọn ènìyàn náà,

tí ẹni tí Ọlọ́run Olúwa ń ṣe.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-