Publicidade

Salmos 4

Fún adarí orin. Pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn. Saamu ti Dafidi.

1 Dá mi lóhùn nígbà tí mo bá pè ọ́,

ìwọ Ọlọ́run òdodo mi.

Fún mi ní ìdáǹdè nínú ìpọ́njú mi;

ṣàánú fún mi, kí o sì gbọ́ àdúrà mi.

2 Báwo ni yóò ṣe pẹ́ tó, ẹ̀yin ọmọ ènìyàn, tí ẹ ó ṣe sọ ògo mi di ìtìjú?

Báwo ni yóò ṣe pẹ́ tó, tí ẹ̀yin yóò ṣe fẹ́ràn ìtànjẹ àti tí ẹ̀yin yóò fi máa wá ọlọ́run èké?

3 Ṣùgbọ́n kí ẹ mọ̀ pé, Olúwa ti ya ẹni olódodo sọ́tọ̀ fún ara rẹ̀;

Olúwa yóò gbọ́ nígbà tí mo bá pè é.

4 Ẹ bínú ẹ má ṣe ṣẹ̀,

nígbà tí ẹ bá wà lórí ibùsùn yín,

ẹ bá ọkàn yín sọ̀rọ̀, kí ó sì dákẹ́ jẹ́.

5 Ẹ rú ẹbọ òdodo

kí ẹ sì gbẹ́kẹ̀lé Olúwa.

6 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ló ń béèrè pé, "Ta ni yóò ṣe rere fún wa?"

Olúwa, jẹ́ kí ojú rẹ mọ́lẹ̀ sí wa lára,

7 Ìwọ ti fi ayọ̀ púpọ̀ kún ọkàn mi

ju ìgbà tí hóró irúgbìn àti wáìnì tuntun wọ́n pọ̀ fún mi lọ.

8 Èmi yóò dùbúlẹ̀, èmi ó sì sùn ní àlàáfíà,

nítorí ìwọ nìkan, Olúwa,

ni o mú mi gbé láìléwu.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-