Publicidade

Salmos 107

1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun;

nítorí ìfẹ́ rẹ̀ dúró láéláé.

2 Jẹ́ kí àwọn ẹni ìràpadà Olúwa kí ó wí báyìí,

àwọn ẹni tí ó rà padà kúrò lọ́wọ́ ọ̀tá,

3 àwọn tí ó kójọ láti ilẹ̀ wọ̀n-ọn-nì,

láti ìlà-oòrùn àti ìwọ̀-oòrùn,

láti àríwá àti Òkun wá.

4 Wọ́n ń rìn káàkiri ní aginjù ní ibi tí ọ̀nà kò sí,

wọn kò rí ọ̀nà lọ sí ìlú níbi tí

wọn ó máa gbé.

5 Ebi ń pa wọn, òǹgbẹ gbẹ wọ́n,

ó sì rẹ ọkàn wọn nínú wọn.

6 Ní ìgbà náà, wọ́n kígbe sókè

Olúwa nínú ìdààmú wọn,

ó sì yọ wọ́n kúrò nínú ìrora wọn

7 Ó fi ọ̀nà títọ́ hàn wọ́n sí ìlú

tí wọn lè máa gbé.

8 Ẹ jẹ́ kí wọn máa yin Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti nítorí iṣẹ́

ìyanu rẹ̀ sí àwọn ọmọ ènìyàn,

9 nítorí tí ó tẹ́ ìfẹ́ ọkàn lọ́run

ó sì fi ìre fún ọkàn tí ebi ń pa.

10 Ọ̀pọ̀ jókòó nínú òkùnkùn àti òjìji ikú,

a dè wọ́n ní ìrora àti ní irin,

11 nítorí tí wọ́n ṣe àìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀

Ọlọ́run, wọ́n kẹ́gàn ìbáwí Ọ̀gá-ògo,

12 Ó sì fi ìkorò rẹ àyà wọn sílẹ̀;

wọn ṣubú, kò sì ṣí ẹni tí

yóò ràn wọ́n lọ́wọ́.

13 Ní ìgbà náà wọ́n ké pe

Olúwa nínú ìdààmú wọn,

ó sì gbà wọ́n nínú ìṣòro wọn

14 Ó mú wọn jáde kúrò nínú

òkùnkùn àti òjìji ikú,

ó sì fa irin tí wọ́n fi dè wọ́n já.

15 Ẹ jẹ́ kí wọn fi ọpẹ́ fún Olúwa! Nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti nítorí iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ sí ọmọ ènìyàn.

16 Nítorí tí ó já ìlẹ̀kùn idẹ wọ̀n-ọn-nì

ó sì ké irin wọn ní agbede-méjì.

17 Ọ̀pọ̀ di aṣiwèrè nítorí ìrékọjá wọn

wọ́n sì pọ́n wọn lójú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn.

18 Wọ́n kọ gbogbo oúnjẹ

wọ́n sì súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà ikú.

19 Nígbà náà wọ́n kígbe sí Olúwa nínú ìṣòro wọn,

ó sì yọ wọ́n nínú ìdààmú wọn.

20 Ó rán ọ̀rọ̀ rẹ̀, ara wọn sì dá

ó sì yọ wọ́n nínú isà òkú.

21 Ẹ jẹ́ kí wọ́n fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀ àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ fún ọmọ ènìyàn.

22 Jẹ́ kí wọn rú ẹbọ ọpẹ́

kí wọn kí ó fi ayọ̀ sọ̀rọ̀ iṣẹ́ rẹ̀.

23 Àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀ lọ sí Òkun nínú ọkọ̀ ojú omi,

wọ́n jẹ́ oníṣòwò nínú omi ńlá.

24 Wọ́n rí iṣẹ́ Olúwa,

àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ nínú ibú.

25 Nítorí tí ó pàṣẹ, ó sì mú ìjì fẹ́

tí ó gbé ríru rẹ̀ sókè.

26 Wọ́n gòkè lọ sí ọ̀run wọ́n sì

tún sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibú:

nítorí ìpọ́njú, ọkàn wọn di omi.

27 Wọ́n ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n bí ọ̀mùtí ènìyàn:

ọgbọ́n wọn sì dé òpin.

28 Nígbà náà wọ́n ń kígbe sókè

Olúwa nínú ìdààmú wọn,

ó sì mú wọn jáde nínú ìṣòro wọn.

29 Ó sọ ìjì di ìdákẹ́rọ́rọ́

bẹ́ẹ̀ ni ríru omi rẹ̀ dúró jẹ́ẹ́.

30 Inú wọn dùn nígbà tí ara wọn balẹ̀,

ó mú wọn lọ sí ibi tí ọkàn wọn lọ.

31 Jẹ́ kí wọn fi ọpẹ́ fún

Olúwa nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ̀

àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ fún ọmọ ènìyàn.

32 Jẹ́ kí wọn gbé e ga ní àárín àwọn ènìyàn

kí wọn kí ó sì yìn ín ní ìjọ àwọn àgbàgbà.

33 Ó sọ odò di aginjù,

àti orísun omi di ilẹ̀ gbígbẹ.

34 Ilẹ̀ eléso di aṣálẹ̀

nítorí ìwà búburú àwọn tí ó wà nínú rẹ̀.

35 O sọ aginjù di adágún omi àti

ilẹ̀ gbígbẹ di orísun omi,

36 níbẹ̀ ó mú ẹni tí ebi ń pa wà,

wọ́n sì pilẹ̀ ibi tí wọn ó máa gbé.

37 Wọn fún irúgbìn, wọ́n sì gbin ọgbà àjàrà

tí yóò máa so èso tí ó dára;

38 Ó bùkún wọn, wọ́n sì pọ̀ sí i ní iye

kò sí jẹ́ kí ẹran ọ̀sìn wọn kí ó dínkù.

39 Nígbà náà, ọjọ́ wọn kúrú,

ìnira, ìpọ́njú àti ìṣòro wọn sì dínkù,

40 ẹni tí ó da ẹ̀gàn lu ọmọ-aládé

ó sì mú wọn rìn níbi tí ọ̀nà kò sí.

41 Ṣùgbọ́n ó gbé aláìní sókè kúrò nínú ìnira

ó mú ìdílé wọn pọ̀ bí agbo ẹran.

42 Àwọn tí ó dúró sì rí i, inú wọn sì dùn

ṣùgbọ́n gbogbo olùṣe búburú yóò pa ẹnu rẹ̀ mọ́.

43 Ẹni tí ó bá gbọ́n, jẹ́ kí ó kíyèsi nǹkan wọ̀nyí

kí ó wo títóbi ìfẹ́ Olúwa.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-