Publicidade

Salmos 5

Fún adarí orin. Fún ohun èlò orin fífọn. Saamu ti Dafidi.

1 Fi etí sí ọ̀rọ̀ mi, Olúwa,

kíyèsi àròyé mi.

2 Fi etí sílẹ̀ sí igbe mi fún ìrànlọ́wọ́,

ọba mi àti Ọlọ́run mi,

nítorí ìwọ ni mo gba àdúrà sí.

3 Ní òwúrọ̀, Olúwa, ìwọ yóò gbọ́ ohùn mi;

ní òwúrọ̀, èmi yóò gbé ẹ̀bẹ̀ mi sí iwájú rẹ̀

èmi yóò sì dúró ní ìrètí.

4 Nítorí ìwọ kì í ṣe Ọlọ́run tí ó ní inú dídùn sí búburú;

bẹ́ẹ̀ ni ẹni ibi kò le è bá ọ gbé.

5 Àwọn agbéraga kò le è dúró

níwájú rẹ̀.

Ìwọ kórìíra gbogbo àwọn aṣebi;

6 ìwọ yóò pa àwọn tí ń ṣe èké run.

Apani àti ẹni ẹ̀tàn ènìyàn

ni Olúwa yóò kórìíra.

7 Ṣùgbọ́n èmi, nípa títóbi àánú rẹ̀,

èmi yóò wá sínú ilé rẹ̀;

ní tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ ni èmi yóò tẹríba

sí ìhà tẹmpili mímọ́ rẹ̀.

8 Tọ́ mi, Olúwa, nínú òdodo rẹ,

nítorí àwọn ọ̀tá mi,

mú ọ̀nà rẹ tọ́ níwájú mi.

9 Kò sí ọ̀rọ̀ kan ní ẹnu wọn tí a lè gbàgbọ́;

ọkàn wọn kún fún ìparun.

Ọ̀nà ọ̀fun wọn ni isà òkú tí ó ṣí sílẹ̀;

pẹ̀lú ahọ́n wọn ni wọ́n ń sọ ẹ̀tàn.

10 Dá wọn lẹ́bi Ọlọ́run!

Jẹ́ kí rìkíṣí wọn jẹ́ ìṣubú wọn.

Lé wọn jáde nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ wọn,

nítorí wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí ọ.

11 Ṣùgbọ́n, jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ó sádi ọ́ kí ó yọ̀;

jẹ kí wọn máa kọrin fún ayọ̀ títí.

Tan ààbò rẹ sórí wọn,

àti àwọn tí ó fẹ́ràn orúkọ rẹ yóò máa yọ̀ nínú rẹ.

12 Dájúdájú, Olúwa, ìwọ bùkún olódodo;

ìwọ fi ojúrere rẹ yí wọn ká bí asà.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-