Publicidade

Salmos 82

Saamu ti Asafu.

1 Ọlọ́run ń ṣàkóso nínú ìpéjọpọ̀ ńlá,

ó ṣe ìdájọ́ láàrín àwọn "ọlọ́run òrìṣà".

2 "Yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò máa gbèjà àwọn aláìṣòdodo

kí ó sì ṣe ojú ìṣáájú sí àwọn ènìyàn búburú?

3 Gbèjà àwọn aláìlágbára àti aláìní baba;

ṣe ìtọ́jú ẹ̀tọ́ àwọn aláìní àti ẹni ìnilára.

4 Gba àwọn aláìlágbára àti aláìní;

gbà wọ́n kúrò lọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú.

5 "Wọn kò mọ̀ ohun kankan,

wọn kò lóye ohun kankan.

Wọn ń rìn kiri nínú òkùnkùn;

à si mí gbogbo ìpìlẹ̀ ayé.

6 "Mo wí pé, ‘Ẹyin ní "Ọlọ́run òrìṣà";

ẹ̀yin ní gbogbo ọmọ Ọ̀gá-ògo jùlọ.’

7 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ó kú bí ènìyàn lásán;

ẹ̀yin ó ṣubú bí ọ̀kan nínú ọmọ-aládé."

8 Dìde, Ọlọ́run, ṣe ìdájọ́ ayé,

nítorí gbogbo orílẹ̀-èdè ni ìní rẹ.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-