Publicidade

Salmos 76

Fún adarí orin. Pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn. Saamu ti Asafu. Orin.

1 Ní Juda ni a mọ Ọlọ́run;

orúkọ rẹ̀ sì lágbára ní Israẹli

2 Àgọ́ rẹ̀ wà ní Salẹmu,

ibùgbé rẹ̀ ni Sioni.

3 Níbẹ̀ ni ó ṣẹ́ ọfà,

asà àti àwọn idà, ohun ìjà ogun. Sela.

4 Ìwọ ni ògo àti ọlá,

ju òkè ńlá ìkógun wọ̀nyí lọ.

5 A kó àwọn alágídí ọkàn ní ìkógun

wọ́n sun oorun ìgbẹ̀yìn wọn;

kò sí ọ̀kan nínú àwọn akọni

tó lè gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè.

6 Ní ìfibú rẹ, Ọlọ́run Jakọbu,

àwọn ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ ogun sì dùbúlẹ̀ síbẹ̀.

7 Ìwọ nìkan ni ó yẹ kí a bẹ̀rù.

Ta ló lé dúró níwájú rẹ, nígbà tí ìwọ bá ń bínú?

8 Ìwọ ń ṣe ìdájọ́ láti ọ̀run,

ilé ayé bẹ̀rù, ó sì dúró jẹ́ẹ́,

9 nígbà tí, ìwọ Ọlọ́run,

bá dìde láti ṣe ìdájọ́,

láti gba àwọn ẹni ìnilára ilẹ̀ náà. Sela.

10 Lóòótọ́, ìbínú rẹ sí àwọn ènìyàn ń mú ìyìn wá fún ọ,

ẹni tí ó yọ nínú ìbínú rẹ ní a dá nígbà tí ìwọ bá fi ìbínú ìyókù di ara rẹ ni àmùrè.

11 Jẹ́ ẹ̀jẹ́ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ kí o sì mú un ṣẹ;

kí gbogbo àwọn tí ó yí i ká

mú ẹ̀bùn wá fún ẹni tí ó tọ́ láti bẹ̀rù.

12 Ó ké ẹ̀mí àwọn aládé kúrò;

àwọn ọba ayé sì ń bẹ̀rù rẹ̀.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-