Publicidade

Salmos 99

1 Olúwa jẹ ọba;

jẹ́ kí ayé kí ó wárìrì

Ó jókòó lórí ìtẹ́ kérúbù

jẹ́ kí ayé kí ó wárìrì.

2 Olúwa tóbi ní Sioni;

Ó sì ga jù gbogbo orílẹ̀-èdè lọ.

3 Kí wọ́n sì yin orúkọ rẹ̀ tí ó tóbi

tí ó ni ẹ̀rù, Mímọ́ ni Òun.

4 Ọba náà ní agbára, ó sì fẹ́ òdodo,

ìwọ fi ìdí àìṣègbè múlẹ̀;

ìwọ ṣe ohun tí ó tọ́ àti ohun tí ó yẹ nínú Jakọbu.

5 Gbígbéga ni Olúwa Ọlọ́run wa

ẹ foríbalẹ̀ níbi ẹsẹ̀ rẹ̀; ó jẹ́ mímọ́.

6 Mose àti Aaroni wà nínú àwọn àlùfáà rẹ̀

Samuẹli wà nínú àwọn tí ó ń ké pe orúkọ rẹ̀

wọ́n ké pe Olúwa, ó sì dá wọn lóhùn.

7 Ó sọ̀rọ̀ sí wọn nínú ọ̀wọ́n àwọsánmọ̀,

wọ́n pa ẹ̀rí rẹ̀ mọ́ àti ìlànà tí ó fún wọn.

8 Olúwa Ọlọ́run wa, ó dá wọn lóhùn;

ó jẹ́ Ọlọ́run tí ó ń dáríjì àwọn ọmọ Israẹli

ìwọ tí ó ń fi ìyà àìṣedéédéé wọn jẹ wọ́n.

9 Gbígbéga ni Olúwa Ọlọ́run wa

kí a sìn ín ní òkè mímọ́ rẹ̀

nítorí Olúwa Ọlọ́run wa jẹ́ mímọ́.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-