Publicidade

Salmos 138

Ti Dafidi.

1 Èmi yóò yìn ọ́ tinútinú mi gbogbo;

níwájú àwọn òrìṣà ni èmi ó kọrin ìyìn sí ọ.

2 Èmi ó máa gbàdúrà sí ìhà tẹmpili mímọ́ rẹ̀

èmi ó sì máa yin orúkọ rẹ

nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ àti òtítọ́ rẹ;

nítorí ìwọ gbé ọ̀rọ̀ rẹ ga ju orúkọ rẹ lọ.

3 Ní ọjọ́ tí mo ké pè é ọ́, ìwọ dá mi lóhùn,

ìwọ sì fi ipa mú mi lára le ní ọkàn mi.

4 Gbogbo àwọn ọba ayé yóò yìn ọ́,

Olúwa, ní ìgbà tí wọn bá gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ.

5 Nítòótọ́, wọn ó máa kọrin ní ipa ọ̀nà Olúwa;

nítorí pé ńlá ni ògo Olúwa.

6 Olúwa tilẹ̀ ga, síbẹ̀ ó júbà àwọn onírẹ̀lẹ̀;

ṣùgbọ́n agbéraga ni ó mọ̀ ní òkèrè réré.

7 Bí èmi tilẹ̀ ń rìn nínú ìpọ́njú ìwọ ni yóò sọ mi di ààyè;

ìwọ ó na ọwọ́ rẹ sí àwọn ọ̀tá mi,

ọwọ́ ọ̀tún rẹ yóò sì gbà mí.

8 Olúwa yóò ṣe ohun tí ń ṣe tèmi láṣepé;

Olúwa, àánú rẹ dúró láéláé;

má ṣe kọ iṣẹ́ ọwọ́ ara rẹ sílẹ̀.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-