Publicidade

Salmos 1

1 Ìbùkún ni fún ọkùnrin náà,

tí kò rìn ní ìmọ̀ àwọn ènìyàn búburú,

ti kò dúró ní ọ̀nà àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀,

tàbí tí kò sì jókòó ní ibùjókòó àwọn ẹlẹ́gàn.

2 Ṣùgbọ́n ayọ̀ inú rẹ̀ wà nínú òfin Olúwa

àti nínú òfin rẹ̀ ni ó ń ṣe àṣàrò ní ọ̀sán àti òru.

3 Ó dàbí igi tí a gbìn sí etí odò tí ń sàn,

tí ń so èso rẹ̀ jáde ní àkókò rẹ̀

tí ewé rẹ̀ kì yóò rẹ̀.

Ohunkóhun tí ó dáwọ́lé, ni yóò máa yọrí sí rere.

4 Kò le rí bẹ́ẹ̀ fún àwọn ènìyàn búburú!

Wọn yóò dàbí ìyàngbò ọkà

tí afẹ́fẹ́ ń fẹ́ dànù.

5 Nítorí náà àwọn ènìyàn búburú kì yóò le è dìde dúró ní ìdájọ́,

bẹ́ẹ̀ ni àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ kì yóò le è dúró ní àwùjọ àwọn olódodo.

6 Nítorí Olúwa ń ṣọ́ ọ̀nà àwọn olódodo,

ṣùgbọ́n ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú ni yóò ṣègbé.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-