Publicidade

Salmos 124

Orin fún ìgòkè. Ti Dafidi.

1 "Ìbá má ṣe pé Olúwa tí ó ti wà fún wa,"

kí ni Israẹli kí ó máa wí nísinsin yìí;

2 ìbá má ṣe pé Olúwa tó wà ní tiwa,

nígbà tí àwọn ènìyàn gbógun sí wa,

3 nígbà náà ni wọn ò bá gbé wà mì láààyè

nígbà tí ìbínú wọn ru sí wa,

4 nígbà náà ni omi

wọ̀n-ọn-nì ìbá bò wá mọ́lẹ̀,

5 nígbà náà ni agbéraga

omi ìbá borí ọkàn wa.

6 Olùbùkún ni Olúwa, tí kò fi wá fún wọ́n

bí ohun ọdẹ fún eyín wọn.

7 Ọkàn wa yọ bí ẹyẹ jáde kúrò nínú okùn apẹyẹ;

okùn já àwa sì yọ.

8 Ìrànlọ́wọ́ wa ń bẹ ní orúkọ Olúwa,

tí ó dá ọ̀run òun ayé.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-