Publicidade

Salmos 20

Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi.

1 Olúwa kí ó gbóhùn rẹ ní ọjọ́ ìpọ́njú;

kí orúkọ Ọlọ́run Jakọbu kí ó dáàbò bò ọ́.

2 Kí ó rán ìrànlọ́wọ́ sí ọ, láti ibi mímọ́

kí ó sì tì ọ́ lẹ́yìn láti Sioni wá.

3 Kí ó sì rántí gbogbo ẹbọ rẹ

kí ó sì gba ẹbọ sísun rẹ. Sela.

4 Kí ó fi fún ọ gẹ́gẹ́ bi ti èrò ọkàn rẹ

kí ó sì mú gbogbo ìmọ̀ rẹ ṣẹ.

5 Àwa yóò hó fún ayọ̀ nígbà tí o bá di aṣẹ́gun

àwa yóò gbé àsíá wa sókè ní orúkọ Ọlọ́run wa.

Olúwa kí ó mú gbogbo ìbéèrè rẹ̀ ṣẹ.

6 Nísinsin yìí, èmi mọ̀ wí pé,

Olúwa pa ẹni àmì òróró rẹ̀ mọ́.

Yóò gbọ́ láti ọ̀run mímọ́ rẹ̀ wá

pẹ̀lú agbára ìgbàlà ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀.

7 Àwọn mìíràn gbẹ́kẹ̀ wọn lé kẹ̀kẹ́, àwọn mìíràn gbẹ́kẹ̀ wọn lé ẹṣin,

ṣùgbọ́n àwa gbẹ́kẹ̀lé orúkọ Olúwa Ọlọ́run wa.

8 Wọ́n wólẹ̀, ní eékún, wọ́n sì ṣubú,

ṣùgbọ́n àwa dìde, a sì dúró ṣinṣin.

9 Olúwa, fi ìṣẹ́gun fún ọba!

Dá wa lóhùn nígbà tí a bá ń kígbe pè!

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-