Publicidade

Salmos 120

Orin fún ìgòkè.

1 Èmi ké pe Olúwa nínú ìpọ́njú mi,

ó sì dá mi lóhùn.

2 Gbà mí, Olúwa, kúrò lọ́wọ́ ètè èké

àti lọ́wọ́ ahọ́n ẹ̀tàn.

3 Kí ni kí a fi fún ọ?

Àti kí ni kí a túnṣe fún ọ,

ìwọ ahọ́n ẹ̀tàn?

4 Òun yóò bá ọ wí pẹ̀lú ọfà mímú ológun,

pẹ̀lú ẹ̀yín iná igi ìgbálẹ̀.

5 Ègbé ni fún mi tí èmi ṣe àtìpó ní Meṣeki,

nítorí èmi gbé nínú àgọ́ ìlú Kedari!

6 Ó ti pẹ́ tí èmi ti ń gbé

láàrín àwọn tí ó kórìíra àlàáfíà.

7 Ènìyàn àlàáfíà ni mí;

ṣùgbọ́n nígbà tí mo bá sọ̀rọ̀, ogun ni dúró fun wọn.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-