Publicidade

Salmos 43

1 Dá mi láre, Ọlọ́run mi,

kí o sì gba ọ̀rọ̀ mi rò lọ́dọ̀ àwọn aláìláàánú orílẹ̀-èdè:

yọ mí kúrò lọ́wọ́ ẹlẹ́tàn àti àwọn ènìyàn búburú.

2 Ìwọ ni Ọlọ́run ibi agbára mi.

Èéṣe tí ìwọ fi kọ̀ mi sílẹ̀?

Èéṣe tí èmi yóò máa rìn nínú ìbìnújẹ́,

nítorí ìnilára lọ́dọ̀ àwọn ọ̀tá?

3 Rán ìmọ́lẹ̀ àti òtítọ́ rẹ jáde,

jẹ́ kí wọn ó máa dáàbò bò mí;

jẹ́ kí wọn mú mi wá sí òkè mímọ́ rẹ,

sí ibi tí ìwọ ń gbé.

4 Nígbà náà ni èmi ó lọ sí ibi pẹpẹ Ọlọ́run,

sí Ọlọ́run ayọ̀ mi àti ìdùnnú mi,

èmi yóò yìn ọ́ pẹ̀lú dùùrù,

ìwọ Ọlọ́run, Ọlọ́run mi.

5 Èéṣe tí o fi ń rẹ̀wẹ̀sì, ìwọ ọkàn mí?

Èéṣe tí ó fi ń ru sókè nínú mi?

Fi ìrètí rẹ sínú Ọlọ́run,

nítorí èmi yóò máa yìn ín, Òun ni

Olùgbàlà mi àti Ọlọ́run mi.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-16_18-40-07-