Publicidade

Salmos 121

Orin fún ìgòkè.

1 Èmi yóò gbé ojú mi sórí òkè wọ̀n-ọn-nì—

níbo ni ìrànlọ́wọ́ mi yóò ti wá?

2 Ìrànlọ́wọ́ mi tí ọwọ́ Olúwa wá,

ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.

3 Òun kì yóò jẹ́ kí ẹsẹ̀ rẹ kí ó yẹ̀;

ẹni tí ó pa ọ́ mọ́ kì í tòògbé.

4 Kíyèsi, ẹni tí ń pa Israẹli mọ́,

kì í tòògbé bẹ́ẹ̀ ni kì í sùn.

5 Olúwa ni olùpamọ́ rẹ;

Olúwa ní òjìji rẹ ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ.

6 Oòrùn kì yóò pa ọ́ ní ìgbà ọ̀sán

tàbí òṣùpá ní ìgbà òru.

7 Olúwa yóò pa ọ́ mọ́ kúrò nínú ibi gbogbo

yóò pa ọkàn rẹ mọ́

8 Olúwa yóò pa àlọ àti ààbọ̀ rẹ mọ́

láti ìgbà yìí lọ àti títí láéláé.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-16_06-50-08-