Publicidade

Salmos 149

1 Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.

Ẹ kọrin tuntun sí Olúwa.

Ẹ yìn ín ní àwùjọ àwọn ènìyàn mímọ́.

2 Jẹ́ kí Israẹli kí ó ní inú dídùn sí ẹni tí ó dá a

jẹ́ kí àwọn ọmọ Sioni kí ó ní

ayọ̀ nínú ọba wọn.

3 Jẹ́ kí wọn kí ó fi ijó yin orúkọ rẹ̀

jẹ́ kí wọn kí ó fi ohun èlò orin kọrin ìyìn sí i.

4 Nítorí Olúwa ní inú dídùn sí àwọn ènìyàn rẹ̀

ó fi ìgbàlà dé àwọn onírẹ̀lẹ̀ ládé.

5 Jẹ́ kí àwọn ènìyàn mímọ́ kí ó yọ̀ nínú ọlá rẹ̀

kí wọn kí ó máa kọrin fún ayọ̀ ní orí ibùsùn wọn.

6 Kí ìyìn Ọlọ́run kí ó wà ní ẹnu wọn

àti idà olójú méjì ní ọwọ́ wọn.

7 Láti gba ẹ̀san lára àwọn orílẹ̀-èdè,

àti ìjìyà lára àwọn ènìyàn,

8 láti fi ẹ̀wọ̀n de àwọn ọba wọn

àti láti fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀

irin de àwọn ọlọ́lá wọn.

9 Láti ṣe ìdájọ́ tí àkọsílẹ̀ rẹ̀ sí wọn

èyí ni ògo àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀.

Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-