Publicidade

Salmos 67

Fún adarí orin. Pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn. Saamu. Orin.

1 Kí Ọlọ́run kí ó ṣàánú fún wa kí ó sì bùkún fún wa,

kí ó sì jẹ́ kí ojú rẹ̀ tàn yí wa ká,

2 kí ọ̀nà rẹ le di mí mọ̀ ní ayé,

ìgbàlà rẹ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.

3 Kí àwọn ènìyàn kí ó yìn ọ́, Ọlọ́run;

kí gbogbo ènìyàn kí ó yìn ọ́!

4 Kí orílẹ̀-èdè kí ó yọ̀, kí ó sì kọrin fún ayọ̀,

nítorí ìwọ fi òdodo darí àwọn ènìyàn,

ìwọ sì jẹ ọba àwọn orílẹ̀-èdè ní ayé.

5 Kí àwọn ènìyàn kí ó yìn ọ́, Ọlọ́run;

kí gbogbo ènìyàn kí ó yìn ọ́. Sela.

6 Nígbà náà ní ilẹ̀ yóò mú ìkórè rẹ̀ wá, Ọlọ́run,

Ọlọ́run wa, yóò bùkún fún wa.

7 Ọlọ́run yóò bùkún fún wa,

àti gbogbo òpin ilẹ̀ ayé yóò sì máa bẹ̀rù rẹ̀.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-