Publicidade

Salmos 140

Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi.

1 Olúwa, gbà mi lọ́wọ́ ọkùnrin búburú u nì,

yọ mí lọ́wọ́ ọkùnrin ìkà a nì,

2 ẹni tí ń ro ìwà búburú ní inú wọn;

nígbà gbogbo ni wọ́n ń rú ìjà sókè sí mi.

3 Wọ́n ti pọ́n ahọ́n wọn bí ejò,

oró paramọ́lẹ̀ ń bẹ ní abẹ́ ètè wọn.

4 Olúwa, pa mí mọ́ kúrò lọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú;

yọ mí kúrò lọ́wọ́ ọkùnrin ìkà a nì

ẹni tí ó ti pinnu rẹ̀ láti bi ìrìn mi ṣubú.

5 Àwọn agbéraga ti dẹkùn sílẹ̀ fún mi àti okùn:

wọ́n ti na àwọ̀n lẹ́bàá ọ̀nà;

wọ́n ti kẹ́kùn sílẹ̀ fún mi.

6 Èmi wí fún Olúwa pé ìwọ ni Ọlọ́run mi;

Olúwa, gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi.

7 Olúwa Olódùmarè, agbára ìgbàlà mi,

ìwọ ni ó bo orí mi mọ́lẹ̀ ní ọjọ́ ìjà.

8 Olúwa, máa ṣe fi ìfẹ́ ènìyàn búburú fún un;

má ṣe kún ọgbọ́n búburú rẹ̀ lọ́wọ́;

kí wọn kí ó máa ba à gbé ara wọn ga. Sela.

9 Bí ó ṣe ti orí àwọn tí ó yí mi káàkiri ni,

jẹ́ kí ète ìka ara wọn kí ó bò wọ́n mọ́lẹ̀.

10 A ó da ẹ̀yin iná sí wọn lára,

Òun yóò wọ́ wọn lọ sínú iná,

sínú ọ̀gbun omi jíjìn,

kí wọn kí ó má ba à le dìde mọ́.

11 Má ṣe jẹ́ kí aláhọ́n búburú fi ẹsẹ̀ múlẹ̀ ní ayé;

ibi ni yóò máa dọdẹ ọkùnrin ìkà nì láti bì í ṣubú.

12 Èmi mọ̀ pé, Olúwa yóò mú ọ̀nà olùpọ́njú dúró,

yóò sì ṣe ẹ̀tọ́ fún àwọn tálákà.

13 Nítòótọ́ àwọn olódodo yóò

máa fi ọpẹ́ fún orúkọ rẹ;

àwọn ẹni dídúró ṣinṣin yóò máa gbé iwájú rẹ.

Veja também

Publicidade
Bíblia Online Bíblia Online

Bíblia Online • Versão: 2026-06-15_21-32-39-